-
Àwọn Tí Ọlọ́run Pè Síbi Àsè KanJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
“Ọkùnrin kan ń se àsè oúnjẹ alẹ́ rẹpẹtẹ, ó sì pe ọ̀pọ̀ èèyàn. Ó rán ẹrú rẹ̀ jáde . . . láti sọ fún àwọn tó pè wá pé, ‘Ẹ máa bọ̀, torí gbogbo nǹkan ti wà ní sẹpẹ́ báyìí.’ Àmọ́ ohun kan náà ni gbogbo wọn ṣe, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í wá àwáwí. Ẹni àkọ́kọ́ sọ fún un pé, ‘Mo ra pápá kan, ó sì yẹ kí n jáde lọ wò ó; jọ̀ọ́, yọ̀ǹda mi.’ Ẹlòmíì sọ pé, ‘Mo ra màlúù mẹ́wàá, mo sì fẹ́ lọ yẹ̀ wọ́n wò; jọ̀ọ́, yọ̀ǹda mi.’ Ẹlòmíì tún sọ pé, ‘Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó ni, torí náà, mi ò ní lè wá.’”—Lúùkù 14:16-20.
Àwáwí tí ò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ ni gbogbo wọn ń wá! Kéèyàn tó ra pápá tàbí màlúù ló yẹ kéèyàn ti wò ó, torí náà, kì í ṣe dandan kí wọ́n lọ wò ó kíákíá, ó ṣe tán, wọ́n ti rà á. Bákan náà, kì í ṣe pé ẹni kẹta ṣẹ̀ṣẹ̀ fẹ́ gbéyàwó, ó ti gbéyàwó, torí náà kò yẹ kíyẹn dí i lọ́wọ́ láti lọ síbi àsè pàtàkì tí wọ́n pè é sí. Nígbà tí ọ̀gá yẹn gbọ́ bí gbogbo wọn ṣe ń wá àwáwí, inú bí i, ó sì sọ fún ẹrú rẹ̀ pé:
-
-
Àwọn Tí Ọlọ́run Pè Síbi Àsè KanJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Àpèjúwe tí Jésù ṣe yìí jẹ́ ká rí bí Jèhófà ṣe lo Jésù láti pe àwọn èèyàn kí wọ́n lè wọ Ìjọba ọ̀run. Àwọn Júù ló kọ́kọ́ pè, ní pàtàkì àwọn aṣáájú ẹ̀sìn. Àmọ́ èyí tó pọ̀ jù nínú wọn ni ò gba ìkésíni yẹn jálẹ̀ gbogbo àkókò tí Jésù fi ṣiṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀. Jésù wá jẹ́ kó ṣe kedere pé tó bá dọjọ́ iwájú, òun ṣì máa pe àwọn tó bá lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ lára àwọn Júù àtàwọn tí kì í ṣe Júù. Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, Ọlọ́run máa pe àwọn èèyàn táwọn Júù ò gbà pé wọ́n lè rí ojúure Ọlọ́run.—Ìṣe 10:28-48.
-