-
‘Ẹ Ní Ìfẹ́ Láàárín Ara Yín’Ilé Ìṣọ́—2003 | February 1
-
-
5, 6. (a) Àwọn àkàwé ṣókí méjì wo ni Jésù ṣe? (b) Kí làwọn àkàwé wọ̀nyí jẹ́ ká mọ̀ nípa Jèhófà?
5 Nígbà tí Jésù fẹ́ kọ́ àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ nípa ojú tí Jèhófà fi ń wo àwọn to ti ṣáko lọ, ó sọ àkàwé kúkúrú méjì. Ọ̀kan dá lórí olùṣọ́ àgùntàn kan. Jésù sọ pé: “Ọkùnrin wo nínú yín tí ó ní ọgọ́rùn-ún àgùntàn, nígbà tí ọ̀kan nínú wọn bá sọnù, tí kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún sílẹ̀ sẹ́yìn ní aginjù, kí ó sì wá ọ̀kan tí ó sọnù lọ títí yóò fi rí i? Nígbà tí ó bá sì ti rí i, a gbé e lé èjìká rẹ̀, a sì yọ̀. Nígbà tí ó bá sì dé ilé, a pe àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti àwọn aládùúgbò rẹ̀ jọ, a sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ bá mi yọ̀, nítorí mo ti rí àgùntàn mi tí ó sọnù.’ Mo sọ fún yín pé báyìí ni ìdùnnú púpọ̀ yóò ṣe wà ní ọ̀run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronú pìwà dà ju lórí mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún àwọn olódodo tí wọn kò nílò ìrònúpìwàdà.”—Lúùkù 15:4-7.
-
-
‘Ẹ Ní Ìfẹ́ Láàárín Ara Yín’Ilé Ìṣọ́—2003 | February 1
-
-
Ó Sọ Nù àmọ́ Ó Ṣì Ṣeyebíye
8. (a) Báwo ni olùṣọ́ àgùntàn àti obìnrin kan ti ṣe nígbà tí nǹkan sọ nù lọ́wọ́ wọn? (b) Kí ni ohun táwọn èèyàn méjì yìí ṣe jẹ́ ká mọ̀ nípa ojú tí wọ́n fi wo ohun tó sọ nù lọ́wọ́ wọn?
8 Inú àkàwé méjèèjì ni nǹkan kan ti sọ nù, àmọ́ kíyè sí ohun táwọn tí nǹkan wọn sọ nù ṣe. Olùṣọ́ àgùntàn náà kò sọ pé: ‘Kí ni màá máa torí àgùntàn kan ṣoṣo ṣe wàhálà sí nígbà tí mo ṣì ní mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún? Ẹyọ kan tó sọ nù yìí ò ba ohunkóhun jẹ́ o jàre.’ Obìnrin náà ò sọ pé: ‘Kí ni màá máa torí ẹyọ owó kan péré da ara mi láàmú sí? Mẹ́sàn-án tí mo ní ṣì tó fún mi o jàre.’ Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni olùṣọ́ àgùntàn náà wá àgùntàn rẹ̀ tó sọ nù bí ẹni pé ẹyọ kan yẹn péré ló ní. Owó ẹyọ kan tó sọ nù lọ́wọ́ obìnrin náà dùn ún wọ akínyẹmí ará bí ẹni pé kò ní òmíràn mọ́. Inú àkàwé méjèèjì lohun tó sọ nù ti ṣeyebíye sí ẹni tó ni ín. Kí lèyí ṣàpèjúwe?
9. Kí ni àníyàn tí olùṣọ́ àgùntàn àti obìnrin náà ṣe ṣàpèjúwe?
9 Kíyè sí bí Jésù ṣe parí àkàwé méjèèjì, ó ní: “Báyìí ni ìdùnnú púpọ̀ yóò ṣe wà ní ọ̀run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronú pìwà dà,” àti “báyìí ni ìdùnnú ṣe máa ń sọ láàárín àwọn áńgẹ́lì Ọlọ́run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronú pìwà dà.” Nítorí náà, dé àyè kan, ńṣe ni àníyàn olùṣọ́ àgùntàn yìí àti ti obìnrin náà ń fi bí ọ̀ràn ṣe máa ń rí lára Jèhófà àtàwọn ìṣẹ̀dá rẹ̀ tó wà lọ́run hàn. Bí nǹkan tó sọ nù ṣe ṣeyebíye lójú olùṣọ́ àgùntàn náà àti obìnrin náà, bẹ́ẹ̀ làwọn tó ti ṣáko lọ tí wọn ò sì bá àwọn èèyàn Ọlọ́run pé jọ mọ́ ṣe ṣeyebíye lójú Jèhófà. (Jeremáyà 31:3) Àwọn èèyàn yìí lè jẹ́ aláìlera nípa tẹ̀mí lóòótọ́, àmọ́ èyí ò fi dandan túmọ̀ sí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń ṣòjòjò nípa tẹ̀mí, síbẹ̀ wọ́n ṣì lè máa pa àwọn òfin Jèhófà mọ́ dé àyè kan. (Sáàmù 119:176; Ìṣe 15:29) Ìdí rèé, bíi ti ìgbà àtijọ́, tí Jèhófà fi ń lọ́ra láti “ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.”—2 Àwọn Ọba 13:23.
10, 11. (a) Irú ojú wo ló yẹ ká máa fi wo àwọn tó ti ṣáko lọ kúrò nínú ìjọ? (b) Gẹ́gẹ́ bí ohun tí àkàwé méjèèjì tí Jésù ṣe fi hàn, báwo la ṣe lè jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé à ń ṣàníyàn nípa wọn?
10 Bíi ti Jèhófà àti Jésù, àwa náà máa ń ṣàníyàn gan-an nípa àwọn tára wọn ò le nípa tẹ̀mí tí wọn kì í sì í wá sí ìjọ Kristẹni mọ́. (Ìsíkíẹ́lì 34:16; Lúùkù 19:10) Ojú àgùntàn tó sọ nù lá fi ń wo àwọn tára wọn ò le nípa tẹ̀mí o, a ò kà wọ́n sí ẹni tó ti re àjò àrèmábọ̀. A kì í ronú pé: ‘Kí la fẹ́ máa torí ẹnì kan ṣoṣo tó ní àìlera tẹ̀mí ṣe wàhálà fún? Ìjọ á kúkú máa lọ bó ṣe yẹ láìsí ẹni náà níbẹ̀.’ Kàkà ká ronú lọ́nà yìí, bíi ti Jèhófà, àwa náà máa ń fojú ẹni tó ṣeyebíye wo àwọn tó ti ṣáko lọ àmọ́ tí wọ́n fẹ́ padà.
-
-
‘Ẹ Ní Ìfẹ́ Láàárín Ara Yín’Ilé Ìṣọ́—2003 | February 1
-
-
Lo Ìdánúṣe
12. Kí ni gbólóhùn náà “wá ọ̀kan tí ó sọnù lọ” jẹ́ ká mọ̀ nípa irú ẹ̀mí tí olùṣọ́ àgùntàn náà ní?
12 Nínú àkàwé àkọ́kọ́, Jésù sọ pé olùṣọ́ àgùntàn náà á “wá ọ̀kan tí ó sọnù lọ.” Olùṣọ́ àgùntàn náà lo ìdánúṣe àti ìsapá ńláǹlà láti wá àgùntàn tó sọ nù ní àwárí. Ipò nǹkan tó le koko, ewu àti ọ̀nà jíjìn kò dá a dúró. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni olùṣọ́ àgùntàn yìí á wá ẹran rẹ̀ “títí yóò fi rí i.”—Lúùkù 15:4.
13. Báwo làwọn olóòótọ́ ayé ọjọ́un ṣe bójú tó àwọn tó jẹ́ aláìlera, báwo la sì ṣe lè tẹ̀ lé irú àwọn àpẹẹrẹ Bíbélì bẹ́ẹ̀?
13 Lọ́nà kan náà, ríran ẹnì kan tó nílò ìṣírí lọ́wọ́ sábà máa ń béèrè pé kí ẹni náà tó fẹ́ ṣèrànwọ́ lo ìdánúṣe. Àwọn olóòótọ́ ayé ọjọ́un mọ̀ bẹ́ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí Jónátánì, tó jẹ́ ọmọ Sọ́ọ̀lù Ọba, kíyè sí i pé Dáfídì ọ̀rẹ́ òun àtàtà nílò ìṣírí, Jónátánì “dìde . . . ó sì lọ sọ́dọ̀ Dáfídì ní Hóréṣì, kí ó bàa lè fún ọwọ́ rẹ̀ lókun nípa ti Ọlọ́run.” (1 Sámúẹ́lì 23:15, 16) Ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún lẹ́yìn náà, nígbà tí Nehemáyà tó jẹ́ Gómìnà kíyè sí i pé ìrẹ̀wẹ̀sì ti bá àwọn kan nínú àwọn ará òun tí wọ́n jẹ́ Júù, ńṣe ló “dìde lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀” tó sì gbà wọ́n níyànjú pé ‘kí wọ́n fi Jèhófà sọ́kàn.’ (Nehemáyà 4:14) Lọ́jọ́ tòní, àwa náà fẹ́ ‘dìde’—ká lo ìdánúṣe—láti fún àwọn tára wọn ò le nípa tẹ̀mí lókun. Àmọ́ àwọn wo ló yẹ kó ṣe èyí nínú ìjọ?
14. Àwọn wo nínú ìjọ Kristẹni ló yẹ kó ṣèrànwọ́ fáwọn aláìlera?
14 Àwọn Kristẹni alàgbà ló ni ẹrù iṣẹ́ náà láti “fún àwọn ọwọ́ tí kò lera lókun [kí wọ́n] sì mú àwọn eékún tí ń gbò yèpéyèpé le gírígírí,” àti láti “sọ fún àwọn tí ń ṣàníyàn nínú ọkàn-àyà pé: ‘Ẹ jẹ́ alágbára. Ẹ má fòyà.’” (Aísáyà 35:3, 4; 1 Pétérù 5:1, 2) Àmọ́ o, wàá kíyè sí i pé kì í ṣe kìkì àwọn alàgbà ni Pọ́ọ̀lù fún nímọ̀ràn láti máa “sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ọkàn tí ó soríkọ́,” àti láti “máa ṣètìlẹyìn fún àwọn aláìlera.” Kàkà bẹ́ẹ̀, gbogbo “ìjọ àwọn ará Tẹsalóníkà” ni Pọ́ọ̀lù darí ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. (1 Tẹsalóníkà 1:1; 5:14) Nítorí náà, gbogbo Kristẹni pátá la yan iṣẹ́ ṣíṣèrànwọ́ fáwọn tára wọn ò le nípa tẹ̀mí fún. Gẹ́gẹ́ bíi ti olùṣọ́ àgùntàn inú àkàwé náà, Kristẹni kọ̀ọ̀kan gbọ́dọ̀ múra tán láti “wá ọ̀kan tí ó sọnù lọ.” Lóòótọ́, láti lè ṣe èyí lọ́nà tó dára jù lọ, èèyàn ní láti fọwọ́ sowọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn alàgbà. Ǹjẹ́ o lè ṣe àwọn ohun kan láti ran ẹnì kan tó ní àìlera tẹ̀mí nínú ìjọ rẹ lọ́wọ́?
-