-
Ó Dé ‘Ìparí Èrò Nínú Ọkàn Rẹ̀’Ilé Ìṣọ́—2008 | October 1
-
-
Nígbà tí Màríà àti Jósẹ́fù máa débẹ̀, ìlú náà ti kún. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn ti ṣáájú wọn dé láti forúkọ sílẹ̀, torí náà kò sáyè fún wọn mọ́ nínú àwọn yàrá táwọn èèyàn máa ń dé sí.b Kò sì síbòmíì tí wọ́n lè sùn sí ju ilé ẹran lọ. Ẹ wo wàhálà ọkàn tó máa bá Jósẹ́fù bó ṣe ń wo ìyàwó rẹ̀ tó ń jẹ̀rora tí ò jẹ rí, tí ìrora náà sì ń pọ̀ sí i. Irú ibí yìí kọ́ ló yẹ kí ọmọ ti mú Màríà.
Gbogbo obìnrin ló máa káàánú Màríà. Ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́rin [4,000] ọdún ṣáájú ìgbà yẹn ni Jèhófà ti sọ tẹ́lẹ̀ pé gbogbo obìnrin láá máa jẹ̀rora nígbà tí wọ́n bá fẹ́ bímọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tá a ti jogún. (Jẹ́nẹ́sísì 3:16) Kò sí ẹ̀rí pé ti Màríà yàtọ̀. Àkọsílẹ̀ tí Lúùkù kọ kò ṣàlàyé ìrora tí Màríà jẹ, ó kàn sọ pé: “Ó sì bí ọmọkùnrin rẹ̀, àkọ́bí.” (Lúùkù 2:7) Báyìí ni Màríà ṣe bí “àkọ́bí” rẹ̀, ìyẹn àkọ́kọ́ lára àwọn ọmọ bíi méje tó bí. (Máàkù 6:3) Àmọ́ ó dájú pé ọmọ yìí máa yàtọ̀ sí gbogbo àwọn tó kù. Yàtọ̀ sí pé ó jẹ́ àkọ́bí Màríà, ó tún jẹ́ “àkọ́bí nínú gbogbo ìṣẹ̀dá,” ìyẹn Ọmọ Ọlọ́run!—Kólósè 1:15.
Bíbélì wá sọ̀rọ̀ kan tí ọ̀pọ̀ èèyàn mọ̀ dáadáa nípa ìtàn Jésù, ó ní: “Ó sì fi àwọn ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran kan.” (Lúùkù 2:7) Èrò àwọn èèyàn kan la sábà máa ń rí nígbà tí wọ́n bá ṣe àwọn fíìmù, tí wọ́n sì ń ya àwọn àwòrán tó dá lórí bí wọ́n ṣe bí Jésù ní ibùjẹ ẹran. Àmọ́ jẹ́ ká ṣàyẹ̀wò ohun tó ṣẹlẹ̀ gan-an. Àpótí táwọn ẹran ti máa ń jẹun ni wọ́n ń pè ní ibùjẹ ẹran. Nítorí náà ilé ẹran ni Jósẹ́fù àti ìyàwó ẹ̀ sùn, irú ibẹ̀ yẹn ò sì lè mọ́ tónítóní láyé ìgbà yẹn àti lóde òní pàápàá, kódà á máa rùn. Ó dájú pé kò sí òbí tó máa fẹ́ lọ bímọ sírú ibẹ̀ yẹn tí ibòmíì tó dáa ju bẹ́ẹ̀ lọ bá wà. Ọ̀pọ̀ òbí ló fẹ́ nǹkan tó dáa jù lọ fáwọn ọmọ wọn. Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ti Ọmọ Ọlọ́run, Màríà àti Jósẹ́fù á fẹ́ káwọn bí i síbi tó dáa jù lọ.
Àmọ́ ṣá o, wọn ò jẹ́ kíyẹn bà wọ́n nínú jẹ́ torí pé ibi tágbára wọn mọ nìyẹn, wọ́n sa gbogbo ipá wọn. Bí àpẹẹrẹ, kíyè sí i pé Màríà ṣètọ́jú ọmọ jòjòló náà, ó fi ọ̀já aṣọ wé e torí òtútù, ó rọra tẹ́ ẹ sí ibùjẹ ẹran, ó sì rí i dájú pé ọmọ náà ò sí nínú ewu. Màríà ò jẹ́ kí ìdààmú tó bá a gbà á lọ́kàn débi tí kò fi ní ráyè ṣe gbogbo ohun tó bá lè ṣe láti tọ́jú ọmọ náà. Òun àti Jósẹ́fù sì tún mọ̀ pé títọ́ ọmọ náà lọ́nà Ọlọ́run lohun tó ṣe pàtàkì jù lọ táwọn lè ṣe fún un. (Diutarónómì 6:6-8) Lóde òní, àwọn òbí tó gbọ́n náà mọ̀ pé kíkọ́ àwọn ọmọ wọn láti jọ́sìn Ọlọ́run ló ṣe pàtàkì jù lọ nínú ayé táwọn èèyàn ò ti ka jíjọ́sìn Ọlọ́run sí nǹkan bàbàrà yìí.
-
-
Ó Dé ‘Ìparí Èrò Nínú Ọkàn Rẹ̀’Ilé Ìṣọ́—2008 | October 1
-
-
b Àṣà ìgbà yẹn ni pé kí ìlú kọ̀ọ̀kan ní ilé táwọn arìnrìn-àjò àtàwọn tó ń kọjá lọ á máa dé sí.
-