-
“Jèhófà, Ọlọ́run Aláàánú àti Olóore Ọ̀fẹ́”Ilé Ìṣọ́—1998 | October 1
-
-
15-17. (a) Kí ni baba náà ṣe nígbà tí ó rí ọmọ rẹ̀? (b) Ki ni aṣọ, òrùka, àti sálúbàtà tí baba pèsè fún ọmọ rẹ̀ túmọ̀ sí? (d) Kí ni ètò tí baba ṣe fún àsè fi hàn?
15 “Nígbà tí ó ṣì wà ní ọ̀nà jíjìn, baba rẹ̀ tajú kán rí i, àánú sì ṣe é, ó sì sáré, ó sì rọ̀ mọ́ ọrùn rẹ̀, ó sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu lọ́nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́. Nígbà náà ni ọmọkùnrin náà wí fún un pé, ‘Baba, èmi ti ṣẹ̀ sí ọ̀run àti sí ọ. Èmi kò yẹ mọ́ ní ẹni tí a ń pè ní ọmọkùnrin rẹ. Fi mí ṣe bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin tí o háyà.’ Ṣùgbọ́n baba náà wí fún àwọn ẹrú rẹ̀ pé, ‘Kíá! ẹ mú aṣọ jáde wá, èyí tí ó dára jù lọ, kí ẹ sì fi wọ̀ ọ́, kí ẹ sì fi òrùka sí ọwọ́ rẹ̀ àti sálúbàtà sí ẹsẹ̀ rẹ̀. Kí ẹ sì mú àbọ́sanra ẹgbọrọ akọ màlúù wá, kí ẹ dúńbú rẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ kí a jẹun, kí a sì gbádùn ara wa, nítorí pé ọmọkùnrin mi yìí kú, ó sì wá sí ìyè; ó sọnù, a sì rí i.’ Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí gbádùn ara wọn.”—Lúùkù 15:20-24.
-
-
“Jèhófà, Ọlọ́run Aláàánú àti Olóore Ọ̀fẹ́”Ilé Ìṣọ́—1998 | October 1
-
-
17 Nígbà tí baba náà pàdé ọmọ rẹ̀, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnu kò ó lẹ́nu lọ́nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́. Lẹ́yìn náà, ó pàṣẹ fún àwọn ẹrú rẹ̀ láti mú aṣọ, òrùka, àti sálúbàtà wá fún ọmọ òun. Aṣọ yìí kì í wulẹ̀ ṣe ẹ̀wù kan lásán, ṣùgbọ́n “èyí tí ó dára jù”—ó ṣeé ṣe kí ó jẹ́ ẹ̀wù àwọ̀lékè tí a kóṣẹ́ sí, irú èyí tí a fi ń ta àlejò pàtàkì lọ́rẹ. Níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé ẹrú kì í sábà fi òrùka sọ́wọ́ tàbí wọ sálúbàtà, baba náà ń mú kí ó ṣe kedere pé òun ń gba ọmọkùnrin òun padà gẹ́gẹ́ bí ojúlówó mẹ́ńbà ìdílé. Ṣùgbọ́n ohun tí baba náà ṣe ṣì kù. Ó pàṣẹ pé kí a ṣayẹyẹ pé ọmọ òun padà wálé. Ó ṣe kedere pé, ọkùnrin yìí kò fi ìlọ́ra dárí ji ọmọ rẹ̀ tàbí pé ó wulẹ̀ pọndandan láti ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí wíwá tí ọmọ rẹ̀ wálé; ó fẹ́ nawọ́ ìdáríjì sí i. Ó mú inú rẹ̀ dùn.
-