-
Ọmọ Tó Sọ Nù Pa Dà WáléJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Ní gbogbo àsìkò yẹn, ẹ̀gbọ́n ọmọ náà wà lóko. Jésù wá sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀ pé: “Bó . . . ṣe dé, tó sún mọ́ ilé, ó gbọ́ orin àti ijó. Torí náà, ó pe ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ sọ́dọ̀, ó sì béèrè ohun tó ń ṣẹlẹ̀. Ìránṣẹ́ náà sọ fún un pé, ‘Àbúrò rẹ ti dé, bàbá rẹ sì dúńbú ọmọ màlúù tó sanra torí ó pa dà rí i ní àlàáfíà.’ Àmọ́ inú bí i, kò sì wọlé. Bàbá rẹ̀ wá jáde, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í bẹ̀ ẹ́. Ó sọ fún bàbá rẹ̀ pé, ‘Wò ó! Ọ̀pọ̀ ọdún yìí ni mo ti ń sìn ọ́, mi ò tàpá sí àṣẹ rẹ rí, síbẹ̀, o ò fún mi ní ọmọ ewúrẹ́ kan rí kí èmi àti àwọn ọ̀rẹ́ mi lè fi gbádùn ara wa. Àmọ́ gbàrà tí ọmọ rẹ yìí dé, ẹni tó lo àwọn ohun ìní rẹ nílòkulò pẹ̀lú àwọn aṣẹ́wó, o dúńbú ọmọ màlúù tó sanra fún un.’”—Lúùkù 15:25-30.
Àwọn wo ló ń ṣe bíi ti ẹ̀gbọ́n ọmọ yìí, tí wọ́n ń ṣàríwísí Jésù torí pé ó ń fàánú hàn sáwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tó sì tún ń gba tàwọn èèyàn rò? Àwọn akọ̀wé òfin àtàwọn Farisí ni. Torí pé wọ́n ń ṣàríwísí Jésù ni Jésù fi sọ àpèjúwe yìí. Torí náà, ó yẹ kí ẹnikẹ́ni tó bá ń bínú pé Ọlọ́run ń fàánú hàn sáwọn èèyàn ronú jinlẹ̀ nípa ẹ̀kọ́ tó wà nínú àpèjúwe yìí.
-
-
Ọmọ Tó Sọ Nù Pa Dà WáléJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Jésù ò sọ ohun tí ẹ̀gbọ́n yẹn ṣe lẹ́yìn ìyẹn. Àmọ́ lẹ́yìn tí Jésù kú, tó sì jíǹde, “ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àlùfáà . . . bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ́wọ́ gba ìgbàgbọ́ náà.” (Ìṣe 6:7) Ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àwọn tó wà níbẹ̀ nígbà tí Jésù sọ àpèjúwe ọmọ tó sọ nù yìí wà lára wọn. Bóyá àwọn náà pe orí ara wọn wálé, tí wọ́n ronú pìwà dà, tí wọ́n sì pa dà sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
-