ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 2. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àti ìwà wo ló ti túbọ̀ ń hàn kedere láti ọdún 1914?

      Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù béèrè lọ́wọ́ ẹ̀ pé: ‘Kí ló máa jẹ́ àmì pé o ti wà níhìn-ín àti ti ìparí ètò àwọn nǹkan?’ (Mátíù 24:3) Jésù wá sọ oríṣiríṣi nǹkan tó máa ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tó bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso lọ́run gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run. Lára àwọn nǹkan tó sọ pé á máa ṣẹlẹ̀ ni ogun, àìtó oúnjẹ àti ìmìtìtì ilẹ̀. (Ka Mátíù 24:7.) Bíbélì tún sọ tẹ́lẹ̀ pé ìwà táwọn èèyàn á máa hù ní “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” máa mú kí nǹkan “nira.” (2 Tímótì 3:1-5) Àwọn nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ láyé àti ìwà àwọn èèyàn, ní pàtàkì látọdún 1914 fi hàn pé òótọ́ lọ̀rọ̀ yìí.

      3. Kí nìdí tí nǹkan fi nira gan-an láyé nígbà tí Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso?

      Láìpẹ́ lẹ́yìn tí Jésù di Ọba Ìjọba Ọlọ́run, ó bá Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù jagun, ó sì ṣẹ́gun wọn. Bíbélì sọ pé ‘a ju Sátánì sí ayé, a sì ju àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ sísàlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀.” (Ìfihàn 12:9, 10, 12) Inú ń bí Sátánì gan-an, torí ó mọ̀ pé òun máa pa run. Ìdí nìyẹn tó fi ń dá wàhálà sílẹ̀ ní gbogbo ayé, tó sì ń mú káyé nira fáwa èèyàn. Abájọ tí wàhálà fi pọ̀ tó báyìí láyé! Àmọ́, Ìjọba Ọlọ́run máa yanjú gbogbo ìṣòro tí Sátánì ti dá sílẹ̀.

  • Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 5. Ọdún 1914 ni ayé yí pa dà bìrí

      Wo FÍDÍÒ yìí.

      FÍDÍÒ: Ọdún 1914 Ni Ayé Yí Pa Dà Bìrí (1:10)

      Jésù sọ bí nǹkan ṣe máa rí láyé tóun bá ti di Ọba. Ka Lúùkù 21:9-11, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

      • Èwo nínú àwọn nǹkan tá a kà yìí lo ti fojú ara ẹ rí tàbí tó o gbọ́ nípa ẹ̀?

      Ọlọ́run mí sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti sọ bí ìwà àti ìṣe àwọn èèyàn ṣe máa rí láwọn ọjọ́ ìkẹyìn ìṣàkóso èèyàn. Ka 2 Tímótì 3:1-5, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

      • Èwo lára àwọn ìwà àti ìṣe yìí lo ti rí?

      Àwòrán: Àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé àti ìwà àwọn èèyàn ní àwọn ọjọ́ ìkẹyìn. 1. Ọ̀gá ológun kan dúró níbi pèpéle kan, ó gbọ́wọ́ sókè, ó ń pariwo sọ̀rọ̀. 2. Àwọn ilé kan wó lulẹ̀ nígbà tí ilẹ̀ mì tìtì. 3. Ọkọ̀ òfúrufú àwọn ológun. 4. Àwọn èèyàn tó fi nǹkan bo imú ń rìn lọ. 5. Ilé gogoro méjì tó wà nílùú New York ń jóná lẹ́yìn táwọn afẹ̀míṣòfò ṣọṣẹ́ níbẹ̀. 6. Ọkùnrin kan ń lo oògùn olóró. 7. Ọkùnrin kan di ọwọ́ ẹ̀ṣẹ́ sí ìyàwó rẹ̀, ó sì ń pariwo mọ́ ọn. 8. Oríṣiríṣi oògùn olóró àti ọtí líle. 9. Àwọn obìnrin méjì wọ aṣọ oge ìgbàlódé, wọ́n sì lo àwọn ohun ọ̀ṣọ́ lóríṣiríṣi, wọ́n ń ya fọ́tò. 10. Ọkùnrin kan ń gbórin jáde níbi táwọn èèyàn ti ń ṣe fàájì, ó gbọ́wọ́ ijó sókè, àwọn èèyàn sì ń jó. 11. Inú ń bí ọkùnrin kan, ó sì ju ohun ìjà oníná síbì kan.
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́