-
Bí Ìràpadà Ṣe Lè Gbà Wá LàIlé Ìṣọ́—2010 | August 15
-
-
A Gbà Wá Lọ́wọ́ Ìrunú Ọlọ́run
4, 5. Kí ló fi hàn pé ìrunú Ọlọ́run ṣì wà lórí ètò àwọn nǹkan búburú ìsinsìnyí?
4 Bíbélì àtàwọn ohun tó ti ṣẹlẹ̀ nínú ìtàn fi hàn pé látìgbà tí Ádámù ti dẹ́ṣẹ̀ ni ìrunú Ọlọ́run ‘ti wà lórí’ ìràn ẹ̀dá èèyàn. (Jòh. 3:36) A sì rí ẹ̀rí èyí kedere ní ti pé bó ti wù kéèyàn pẹ́ láyé tó, ikú ló máa gbẹ̀yìn rẹ̀. Àkóso tí Sátánì gbé kalẹ̀ láti ta ko Ọlọ́run ti kùnà ní gbogbo ọ̀nà torí pé kò lè dáàbò bo aráyé kúrò lọ́wọ́ àwọn ìyọnu àjálù tó ń lọ lọ́wọ́ báyìí, kò sì sí ìjọba èèyàn kankan tó lè pèsè àwọn ohun kòṣeémánìí tí gbogbo àwọn tó ń ṣàkóso lé lórí nílò. (1 Jòh. 5:19) Ìyẹn ni ogun, ìwà ọ̀daràn àti òṣì fi ń fojú aráyé rí màbo.
-
-
Bí Ìràpadà Ṣe Lè Gbà Wá LàIlé Ìṣọ́—2010 | August 15
-
-
7 Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé Jésù “dá wa nídè kúrò nínú ìrunú tí ń bọ̀.” (1 Tẹs. 1:10) Nígbà tí Jèhófà bá tú èyí tó gbẹ̀yìn lára ìrunú rẹ̀ jáde, ó máa yọrí sí ìparun àìnípẹ̀kun fún àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tí kò bá ronú pìwà dà. (2 Tẹs. 1:6-9) Ta ló máa yè bọ́? Bíbélì sọ pé: “Ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú Ọmọ ní ìyè àìnípẹ̀kun; ẹni tí ó bá ń ṣàìgbọràn sí Ọmọ kì yóò rí ìyè, ṣùgbọ́n ìrunú Ọlọ́run wà lórí rẹ̀.” (Jòh. 3:36) Bẹ́ẹ̀ ni, gbogbo àwọn tó bá wà láàyè tí wọ́n sì ń lo ìgbàgbọ́ nínú Jésù àti ìràpadà máa yè bọ́ nígbà tí Ọlọ́run bá tú èyí tó gbẹ̀yìn lára ìrunú rẹ̀ jáde.
-