-
Àwọn Kristian Obìnrin yẹ fún Ọlá àti Ọ̀wọ̀Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 15
-
-
1, 2. (a) Ìdàníyàn wo ni ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ Jesu pẹ̀lú obìnrin ará Samaria létí kànga fà, èésìtiṣe? (Tún wo àkíyèsí ẹsẹ̀ ìwé.) (b) Kí ni Jesu ṣàṣefihàn rẹ̀ nípa wíwàásù fún obìnrin ará Samaria?
NÍ ÌDÍ kànga àtijọ́ kan lẹ́bàá ìlú-ńlá Sikari ní ìgbà òṣùpá ní apá ìparí 30 C.E., Jesu ṣí bí ó ti lérò pé a gbọ́dọ̀ bá àwọn obìnrin lò payá. Ó ti lo òwúrọ̀ láti rìn jákèjádò Samaria orílẹ̀-èdè olókè náà ó sì darí wá sí ìdí kànga pẹ̀lú àárẹ̀, ebi, àti òùngbẹ. Bí ó ti jókòó sẹ́bàá kànga náà, obìnrin ará Samaria kan wá láti fa omi. Jesu wí fún un pé: “Fún mi mu.” Obìnrin náà ti níláti wò ó pẹ̀lú ìyàlẹ́nu. Ó béèrè pé: “Èétirí tí iwọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Júù ni ọ́, fi ń béèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi, nígbà tí mo jẹ́ obìnrin ará Samaria?” Lẹ́yìn náà, nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ padà dé láti ibi tí wọ́n ti lọ ra oúnjẹ, ó yà wọ́n lẹ́nu, ní ṣíṣe kàyéfì nípa ìdí tí Jesu fi “ń bá obìnrin sọ̀rọ̀.”—Johannu 4:4-9, 27.
2 Kí ni ó fa ìbéèrè obìnrin yìí àti àníyàn àwọn ọmọ-ẹ̀yìn? Ó jẹ́ ará Samaria, àwọn Júù kì í sìí ní ìbálò kankan pẹ̀lú àwọn ará Samaria. (Johannu 8:48) Ṣùgbọ́n ẹ̀rí fi hàn pé ìdí mìíràn wà fún àníyàn náà. Ní àkókò náà, àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn rabi kò fún kí àwọn ọkùnrin máa bá àwọn obìnrin sọ̀rọ̀ ní gbangba ní ìṣírí.a Síbẹ̀, Jesu wàásù ní gbangba fún obìnrin olóòótọ́-ọkàn yìí, ó tilẹ̀ ṣí i payá fún un pé òun ni Messia náà. (Johannu 4:25, 26) Jesu tipa báyìí fi hàn pé àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu, títí kan àwọn wọnnì tí ń rẹ àwọn obìnrin sílẹ̀ kò lè ká òun lọ́wọ́ kò. (Marku 7:9-13) Ní òdìkejì rẹ̀, nípa ohun tí ó ṣe àti nípa ohun tí ó fi kọ́ni, Jesu fi hàn pé àwọn obìnrin ni a gbọ́dọ̀ bálò pẹ̀lú ọlá àti ọ̀wọ̀.
-
-
Àwọn Kristian Obìnrin yẹ fún Ọlá àti Ọ̀wọ̀Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 15
-
-
a Ìwé gbédègbẹyọ̀ The International Standard Bible Encyclopedia ṣàlàyé pé: “Àwọn obìnrin kì í bá àwọn àlejò ọkùnrin jẹun, a kò sì fún àwọn ọkùnrin ní ìṣírí láti máa bá àwọn obìnrin sọ̀rọ̀. . . . Bíbá obìnrin sọ̀rọ̀ ní gbangba ní pàtàkì jẹ́ ìwà láìfí atinilójú.” Ìwé The Mishnah ti àwọn Júù, tí ó jẹ́ àkójọpọ̀ ẹ̀kọ́ àwọn rabi, gbani nímọ̀ràn pé: “Sọ̀rọ̀ mọníwọ̀n pẹ̀lú àwọn obìnrin. . . . Ẹni tí kò bá sọ̀rọ̀ mọníwọ̀n pẹ̀lú àwọn obìnrin ń mú ègún wá sí orí ara rẹ̀ ó sì ń ṣàìnáání ìkẹ́kọ̀ọ́ Òfin yóò sì jogún Gehenna nígbẹ̀yìn gbẹ́yín.”—Aboth 1:5.
-