-
“Èèyàn Kankan Ò Sọ̀rọ̀ Báyìí Rí”Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Àwọn kan lára àwọn tó ń tẹ́tí sọ́rọ̀ Jésù sọ pé: “Wòlíì náà nìyí lóòótọ́.” Ó dájú pé àsọtẹ́lẹ̀ tó sọ̀rọ̀ nípa wòlíì tó tóbi ju Mósè ni wọ́n ń tọ́ka sí. Àwọn míì sọ pé: “Kristi náà nìyí.” Àmọ́ àwọn míì sọ pé: “Gálílì kọ́ ni Kristi ti máa jáde wá, àbí ibẹ̀ ni? Ṣebí ìwé mímọ́ sọ pé látinú ọmọ Dáfídì ni Kristi ti máa wá, ó sì máa wá láti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, abúlé tí Dáfídì wà tẹ́lẹ̀?”—Jòhánù 7:40-42.
-
-
“Èèyàn Kankan Ò Sọ̀rọ̀ Báyìí Rí”Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Lóòótọ́, Ìwé Mímọ́ ò sọ ní tààràtà pé wòlíì kan máa wá láti Gálílì. Síbẹ̀ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ́ka sí i pé Kristi máa wá látibẹ̀, torí ó sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn èèyàn máa rí “ìmọ́lẹ̀ tó mọ́lẹ̀ yòò” ní “Gálílì àwọn orílẹ̀-èdè.” (Àìsáyà 9:1, 2; Mátíù 4:13-17) Bákan náà, àsọtẹ́lẹ̀ nípa bí wọ́n ṣe máa bí Jésù ṣẹ torí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ni wọ́n bí i sí, àtọmọdọ́mọ Dáfídì sì ni. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ṣeé ṣe káwọn kan lára àwọn Farisí mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, ó jọ pé àwọn gan-an ló ń tan oríṣiríṣi ọ̀rọ̀ òdì kálẹ̀ nípa Jésù.
-