-
Ẹ Ṣe Iyebíye Lójú Ọlọrun!Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | April 1
-
-
1. Báwo ni ìhùwàsí Jesu sí àwọn ènìyàn gbáàtúù ti ọjọ́ rẹ̀ ṣe yàtọ̀ sí ti àwọn Farisi?
WỌ́N lè rí i ní ojú rẹ̀. Ọkùnrin yìí, Jesu, kò dàbí àwọn aṣáájú ìsìn wọn rárá; ó bìkítà. Àánú àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe é nítorí pé “a bó wọn láwọ a sì fọ́n wọn ká bí awọn àgùtàn tí kò ní olùṣọ́ àgùtàn.” (Matteu 9:36) A retí pé kí àwọn aṣáájú ìsìn wọn jẹ́ àwọn olùṣọ́ àgùtàn onífẹ̀ẹ́, tí wọ́n ń ṣojú fún Ọlọrun onífẹ̀ẹ́, tí ó ní àánú. Kàkà bẹ́ẹ̀, wọn fojú tẹ́ḿbẹ́lú àwọn gbáàtúù gẹ́gẹ́ bí aláìníláárí—àti ẹni ègún!a (Johannu 7:47-49; fiwé Esekieli 34:4.) Ní kedere, irú ojú-ìwòye tí ó lọ́, tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu bẹ́ẹ̀ yàtọ̀ pátápátá sí ojú-ìwòye Jehofa nípa àwọn ènìyàn rẹ̀. Ó ti sọ fún Israeli, orílẹ̀-èdè rẹ̀ pé: “Èmi fi ìfẹ́ni ayérayé fẹ́ ọ.”—Jeremiah 31:3.
-
-
Ẹ Ṣe Iyebíye Lójú Ọlọrun!Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | April 1
-
-
a Ní tòótọ́, wọ́n dá ṣíọ̀ àwọn tálákà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ bíi “ʽam-ha·ʼaʹrets,” tàbí “àwọn ènìyàn ilẹ̀.” Gẹ́gẹ́ bí ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ kan ṣe sọ, àwọn Farisi kọ́ni pé ẹnì kan kò gbọdọ̀ fi ohun tí ó bá níyelórí síkàáwọ́ àwọn wọ̀nyí, kò sì gbọdọ̀ gba ìrírí wọn gbọ́, tàbí gbà wọ́n lálejò, tàbí jẹ́ àlejò wọn, tàbí kí ó tilẹ̀ ra nǹkan lọ́wọ́ wọn. Àwọn aṣáájú ìsìn wí pé bí ọmọbìnrin ẹnì kan bá lọ fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò dàbí yíyọ̀ǹda kí ẹnì kan kojú ẹranko ẹhànnà láìní ohun ìgbèjà.
-