ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • Ẹ̀kọ́ 31. Jésù Kristi ti di Ọba ní ọ̀run, ó dúró síwájú Jèhófà tó wà nínú ògo rẹ̀.

      Ẹ̀KỌ́ 31

      Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?

      Ọ̀rọ̀ nípa Ìjọba Ọlọ́run ni ohun pàtàkì tí Bíbélì dá lé. Ìjọba yẹn ni Jèhófà máa lò láti sọ ayé di Párádísè pa dà. Kí ni Ìjọba Ọlọ́run? Báwo la ṣe mọ̀ pé ó ti ń ṣàkóso báyìí? Àwọn nǹkan wo ló ti ṣe? Àwọn nǹkan wo ló sì máa ṣe lọ́jọ́ iwájú? A máa rí ìdáhùn àwọn ìbéèrè yìí nínú ẹ̀kọ́ yìí àtàwọn ẹ̀kọ́ méjì tó tẹ̀ lé e.

      1. Kí ni Ìjọba Ọlọ́run, ta sì ni Ọba Ìjọba náà?

      Ìjọba Ọlọ́run jẹ́ ìjọba kan tí Jèhófà Ọlọ́run gbé kalẹ̀ ní ọ̀run. Jésù Kristi ni Ọba Ìjọba náà, àtọ̀run ló sì ti ń ṣàkóso. (Mátíù 4:17; Jòhánù 18:36) Bíbélì sọ pé Jésù “máa jẹ Ọba . . . títí láé.” (Lúùkù 1:32, 33) Torí pé Jésù ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run, ó máa ṣàkóso gbogbo àwọn tó wà láyé.

      2. Àwọn wo ló máa ṣàkóso pẹ̀lú Jésù?

      Jésù nìkan kọ́ ló máa dá ṣàkóso. Àwọn èèyàn látinú “gbogbo ẹ̀yà àti ahọ́n àti èèyàn àti orílẹ̀-èdè . . . máa ṣàkóso bí ọba lé ayé lórí.” (Ìfihàn 5:9, 10) Àwọn mélòó ló máa ṣàkóso pẹ̀lú Kristi? Látìgbà tí Jésù ti wá sáyé, àìmọye èèyàn ló ti di Kristẹni. Àmọ́, àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) péré lára wọn ló máa ṣàkóso pẹ̀lú Jésù lọ́run. (Ka Ìfihàn 14:1-4.) Gbogbo àwọn Kristẹni tó kù láyé sì máa jẹ́ ọmọ Ìjọba Ọlọ́run.​—Sáàmù 37:29.

      3. Kí ló mú kí Ìjọba Ọlọ́run dáa ju ìjọba èèyàn lọ?

      Nígbà míì, a lè rí àwọn kan lára àwọn tó ń ṣàkóso tí wọ́n ń gbìyànjú láti ṣohun tó dáa fáwọn aráàlú, àmọ́ agbára wọn kì í gbé e láti ṣe gbogbo ohun tó dáa tí wọ́n ní lọ́kàn. Tó bá yá, ẹlòmíì á rọ́pò wọn, onítọ̀hún sì lè má ní ire ará ìlú lọ́kàn. Àmọ́ ní ti Jésù tó jẹ́ Ọba Ìjọba Ọlọ́run, kò sẹ́ni tó lè rọ́pò ẹ̀ tàbí tó lè gba ìjọba lọ́wọ́ ẹ̀. Ọlọ́run ti “gbé ìjọba kan kalẹ̀, tí kò ní pa run láé.” (Dáníẹ́lì 2:44) Gbogbo ayé ni Jésù máa ṣàkóso, kò sì ní ṣojúsàájú. Kò mọ síbẹ̀ o, ó nífẹ̀ẹ́ wa, olóore ni, ìdájọ́ òdodo ló máa ń ṣe, ó sì máa kọ́ àwọn èèyàn pé káwọn náà nífẹ̀ẹ́ àwọn míì, kí wọ́n máa ṣoore, kí wọ́n sì máa ṣe ìdájọ́ òdodo.​—Ka Àìsáyà 11:9.

      KẸ́KỌ̀Ọ́ JINLẸ̀

      Jẹ́ ká wo ìdí tí Ìjọba Ọlọ́run fi dáa ju ìjọba èèyàn lọ.

      Jésù Kristi ń ṣàkóso ayé látorí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Àwọn tí wọ́n máa bá a ṣàkóso wà lórí ìjókòó lẹ́yìn rẹ̀. Ògo Jèhófà ń tàn yòò lẹ́yìn wọn.

      4. Ìjọba kan tó lágbára máa ṣàkóso gbogbo ayé

      Jésù lágbára ju gbogbo àwọn tó ti ṣàkóso láyé lọ. Ka Mátíù 28:18, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

      • Kí ló mú kí àṣẹ Jésù ju ti àwọn èèyàn tó jẹ́ alákòóso lọ?

      Ní ti ìjọba èèyàn, tẹ́nì kan bá ṣàkóso lónìí, ẹlòmíì á gbà á lọ́la, ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ló sì ti ní apá ibi tí àkóso ẹ̀ dé. Àmọ́ Ìjọba Ọlọ́run ńkọ́? Ka Dáníẹ́lì 7:14, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

      • Kí nìdí tó fi dáa gan-an pé Ìjọba Ọlọ́run ‘kò ní pa run’?

      • Kí nìdí tó fi dáa gan-an pé gbogbo ayé ni Ìjọba Ọlọ́run á máa ṣàkóso?

      5. Ìjọba èèyàn gbọ́dọ̀ dópin

      Kí nìdí tí Ìjọba Ọlọ́run fi gbọ́dọ̀ rọ́pò ìjọba èèyàn? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?​—Àyọlò (1:41)

      • Àkóbá wo ni ìjọba èèyàn ti ṣe fún aráyé?

      Ka Oníwàásù 8:9, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

      • Ṣé o gbà pé ó yẹ kí Ìjọba Ọlọ́run rọ́pò ìjọba èèyàn? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?

      6. Ọ̀rọ̀ wa yé Jésù àtàwọn tó máa bá a ṣàkóso

      Torí pé Jésù Ọba wa ti gbé ayé rí gẹ́gẹ́ bí èèyàn, ó lè “bá wa kẹ́dùn fún àwọn àìlera wa.” (Hébérù 4:15) Bákan náà, “látinú gbogbo ẹ̀yà àti ahọ́n àti èèyàn àti orílẹ̀-èdè” ni Jèhófà ti yan àwọn ọkùnrin àti obìnrin olóòótọ́ tí iye wọn jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) tí wọ́n máa bá Jésù ṣàkóso.​—Ìfihàn 5:9.

      • Ṣé ọkàn ẹ balẹ̀ bó o ṣe mọ̀ pé Jésù àti gbogbo àwọn tó máa bá a ṣàkóso mọ bí nǹkan ṣe máa ń rí lára àwa èèyàn? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?

      Àwọn ẹni àmì òróró tí Ọlọ́run ti ń yàn látìgbà àtijọ́ títí di òde òní. Inú gbogbo ẹ̀yà àti èdè ni Ọlọ́run ti yàn wọ́n.

      Jèhófà ti yan àwọn ọkùnrin àti obìnrin látinú gbogbo ẹ̀yà àti orílẹ̀-èdè láti ṣàkóso pẹ̀lú Jésù

      7. Àwọn òfin Ìjọba Ọlọ́run dáa ju ti ìjọba èèyàn lọ

      Ìjọba èèyàn máa ń ṣe àwọn òfin tí wọ́n gbà pé ó máa ṣe aráàlú láǹfààní tó sì máa dáàbò bò wọ́n. Bákan náà, Ìjọba Ọlọ́run ní àwọn òfin tí àwọn ọmọ Ìjọba Ọlọ́run náà gbọ́dọ̀ máa tẹ̀ lé. Ka 1 Kọ́ríńtì 6:9-​11, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

      • Báwo lo ṣe rò pé ayé máa rí lọ́jọ́ iwájú nígbà tí gbogbo èèyàn bá ń tẹ̀ lé àwọn òfin Ọlọ́run?a

      • Ṣé o rò pé ó bọ́gbọ́n mu bí Jèhófà ṣe sọ pé káwọn ọmọ Ìjọba Ọlọ́run máa tẹ̀ lé àwọn òfin yìí? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?

      • Báwo la ṣe mọ̀ pé àwọn tí kì í tẹ̀ lé àwọn òfin yìí lè yí pa dà?​—Wo ẹsẹ 11.

      Ọlọ́pàá kan dá mọ́tò dúró ní oríta kan táwọn èèyàn ti ń lọ tí wọ́n ń bọ̀. Àwọn èèyàn lọ́mọdé àti lágbá ń sọdá títì.

      Ìjọba èèyàn máa ń ṣe àwọn òfin tí wọ́n gbà pé ó máa ṣe aráàlú láǹfààní tó sì máa dáàbò bò wọ́n. Àmọ́ àwọn òfin Ìjọba Ọlọ́run ṣàǹfààní gan-an ju ti ìjọba èèyàn lọ

      ẸNÌ KAN LÈ BÉÈRÈ PÉ: “Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?”

      • Kí lo máa sọ?

      KÓKÓ PÀTÀKÌ

      Ìjọba Ọlọ́run jẹ́ ìjọba kan tí Ọlọ́run fúnra ẹ̀ gbé kalẹ̀ ní ọ̀run, ó sì máa ṣàkóso lórí gbogbo ayé.

      Kí lo rí kọ́?

      • Àwọn wo ló máa jẹ́ alákòóso Ìjọba Ọlọ́run?

      • Kí ló mú kí Ìjọba Ọlọ́run dáa ju ìjọba èèyàn lọ?

      • Kí ni díẹ̀ lára àwọn nǹkan ti Jèhófà fẹ́ káwọn ọmọ Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe?

      Ohun tó yẹ kó o ṣe

      ṢÈWÁDÌÍ

      Ka ìwé yìí kó o lè mọ ibi tí Jésù sọ pé Ìjọba Ọlọ́run wà.

      “Ṣé Inú Ọkàn Rẹ Ni Ìjọba Ọlọ́run Wà?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

      Kí nìdí tó fi jẹ́ pé Ìjọba Ọlọ́run làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń fi gbogbo ọkàn wa tì lẹ́yìn dípò ìjọba èèyàn?

      Ìjọba Ọlọ́run Ni Wọ́n Fara Mọ́ (1:43)

      Ka ìwé yìí kó o lè mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) tí Jèhófà yàn láti ṣàkóso pẹ̀lú Jésù.

      “Àwọn Wo Ló Ń Lọ sí Ọ̀run?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

      Kí ló mú kí obìnrin kan tó wà lẹ́wọ̀n gbà pé Ọlọ́run nìkan ló lè mú ìrẹ́jẹ kúrò láyé?

      “Mo Ti Wá Mọ Bí Àìṣẹ̀tọ́ Ṣe Máa Dópin” (Jí!, July-September, 2011)

      a A máa ṣàlàyé àwọn kan lára òfin yìí tá a bá dé Apá 3.

  • Ohun Tó Túmọ̀ Sí Láti Má Ṣe Dá Sí Ogun àti Ọ̀rọ̀ Òṣèlú
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • Ẹ̀kọ́ 45. Ọ̀dọ́bìnrin Kristẹni kan ò bá wọn kí àsíá, kò sì fọwọ́ sí àyà bíi tàwọn ọmọléèwé tó kù, àmọ́ ó dìde dúró tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ nígbà tí wọ́n ń ka ẹ̀jẹ́ orílẹ̀-èdè.

      Ẹ̀KỌ́ 45

      Ohun Tó Túmọ̀ Sí Láti Má Ṣe Dá Sí Ogun àti Ọ̀rọ̀ Òṣèlú

      Jésù sọ pé àwọn ọmọ ẹ̀yìn òun ò gbọ́dọ̀ jẹ́ “apá kan ayé.” (Jòhánù 15:19) Lára ohun tí èyí túmọ̀ sí ni pé wọn ò gbọ́dọ̀ dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú àti ogun. Ká sòótọ́, kò rọrùn láti má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Àwọn èèyàn lè máa fi wá ṣe yẹ̀yẹ́ torí pé a ò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Kí la lè ṣe tá ò fi ní máa dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú ká sì jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà Ọlọ́run?

      1. Èrò wo làwa Kristẹni tòótọ́ ní nípa ìjọba èèyàn?

      Àwa Kristẹni máa ń bọ̀wọ̀ fún ìjọba. A máa ń ṣègbọràn sí ohun tí Jésù sọ pé: “Ẹ san àwọn ohun ti Késárì pa dà fún Késárì.” Ọ̀nà tá à ń gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé a máa ń ṣègbọràn sí òfin orílẹ̀-èdè, irú bí òfin tó sọ pé ká máa san owó orí. (Máàkù 12:17) Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà ló gba àwọn ìjọba èèyàn láyè láti máa ṣàkóso. (Róòmù 13:1) Torí náà, a mọ̀ pé ó níbi tí agbára wọn mọ. Ó sì dá wa lójú pé Ìjọba Ọlọ́run nìkan ló lè yanjú gbogbo ìṣòro tó wà láyé.

      2. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a ò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Bíi ti Jésù, a kì í dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Nígbà táwọn kan rí ọ̀kan lára iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe, wọ́n fẹ́ fi jọba, àmọ́ kò gbà fún wọn. (Jòhánù 6:15) Kí nìdí tí Jésù ò fi gbà? Ó sọ pé, “Ìjọba mi kì í ṣe apá kan ayé yìí.” (Jòhánù 18:36) Torí pé ọmọlẹ́yìn Jésù ni wá, àwọn nǹkan kan wà tá a gbọ́dọ̀ yẹra fún ká lè fi hàn pé a ò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Bí àpẹẹrẹ, a kì í lọ́wọ́ sí ogun. (Ka Míkà 4:3.) A máa ń bọ̀wọ̀ fún àwọn àmì orílẹ̀-èdè bí àsíá, àmọ́ a kì í júbà wọn. (1 Jòhánù 5:21) A kì í dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kankan, bẹ́ẹ̀ la kì í ta kò wọ́n. Bákan náà, a kì í dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú láwọn ọ̀nà èyíkéyìí míì. Ńṣe ni èyí ń fi hàn pé Ìjọba Ọlọ́run nìkan la fara mọ́.

      KẸ́KỌ̀Ọ́ JINLẸ̀

      Jẹ́ ká kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn nǹkan tó lè fẹ́ mú ká dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú àtàwọn nǹkan tó lè ràn wá lọ́wọ́ láti ṣèpinnu táá múnú Jèhófà dùn.

      Ọkùnrin kan tí kò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Kò fọkàn sí ìlérí táwọn olóṣèlú ń ṣe bí wọ́n ṣe ń bá àwọn alátìlẹyìn wọn sọ̀rọ̀ lọ́tùn-ún lósì.

      3. Àwọn Kristẹni tòótọ́ kì í dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú

      Jésù àtàwọn ọmọlẹ́yìn ẹ̀ fàpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ fún wa. Ka Róòmù 13:1, 5-7 àti 1 Pétérù 2:13, 14. Lẹ́yìn náà, wo FÍDÍÒ yìí kó o sì dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Àwọn Kristẹni Tòótọ́ Kì Í Dá Sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú​—Apá 1 (4:28)

      • Kí nìdí tó fi yẹ ká máa bọ̀wọ̀ fáwọn aláṣẹ?

      • Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà fi hàn pé a tẹrí ba fún wọn?

      Nígbà ogun, àwọn orílẹ̀-èdè kan máa ń sọ pé àwọn kì í dá sí ogun, àmọ́ wọ́n máa ń fi owó tàbí àwọn ohun ìjà ṣètìlẹyìn fáwọn tó ń jagun. Ṣé a lè sọ pé wọn ò dá sí ogun lóòótọ́? Kí ló túmọ̀ sí láti má ṣe dá sí ogun tàbí ọ̀rọ̀ òṣèlú? Ka Jòhánù 17:16. Lẹ́yìn náà, wo FÍDÍÒ yìí kó o sì dáhùn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Àwọn Kristẹni Tòótọ́ Kì Í Dá Sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú​—Apá 2 (3:11)

      • Kí ló túmọ̀ sí láti má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Kí ló yẹ ká ṣe táwọn aláṣẹ bá sọ pé ká ṣe ohun tó ta ko òfin Ọlọ́run? Ka Ìṣe 5:28, 29. Lẹ́yìn náà, wo FÍDÍÒ yìí kó o sì dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Àwọn Kristẹni Tòótọ́ Kì Í Dá Sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú​—Apá 3 (1:18)

      • Tí ìjọba bá ní ká ṣe ohun tí Ọlọ́run ò fẹ́, ta ló yẹ ká ṣègbọràn sí?

      • Ṣé o lè sọ àwọn àpẹẹrẹ ohun tí ìjọba lè ní káwa Kristẹni ṣe àmọ́ tá ò ní ṣègbọràn sí wọn?

      4. Má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú nínú èrò àti ìṣe rẹ

      Ka 1 Jòhánù 5:21. Lẹ́yìn náà, wo FÍDÍÒ yìí kó o sì dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Ìdí Tí Àwa Kristẹni Tòótọ́ Fi Nílò Ìgboyà​—Láti Má Ṣe Dá Sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú (2:49)

      • Kí nìdí tí Ayenge fi pinnu pé òun ò ní dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú, òun ò sì ní tẹrí ba fún àsíá orílẹ̀-èdè?

      • Ṣé o rò pé ìpinnu tó ṣe yẹn bọ́gbọ́n mu?

      Àwọn nǹkan míì wo ló lè ṣẹlẹ̀ tó lè fẹ́ mú ká dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Àwọn Ẹ̀kọ́ Látinú Ilé Ìṣọ́​—Má Ṣe Dá sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú Tàbí Ogun (5:16)

      • Tó bá dọ̀rọ̀ eré ìdárayá, kí la lè ṣe ká má bàa ṣohun tó fi hàn pé a ka orílẹ̀-èdè wa sí pàtàkì ju àwọn orílẹ̀-èdè míì lọ?

      • Kí la lè ṣe tá ò fi ní dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tó bá tiẹ̀ jẹ́ pé ohun táwọn olóṣèlú fẹ́ ṣe máa pa wá lára tàbí ṣe wá láǹfààní?

      • Báwo ni ohun táwọn oníròyìn ń gbé jáde àtàwọn tá à ń bá kẹ́gbẹ́ ṣe lè mú ká dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Àwòrán: 1. Àwọn ará ìlú ń wọ́de, wọ́n gbé àwọn pátákó tí wọ́n kọ ọ̀rọ̀ sí dání láti fi hàn pé inú ń bí wọn gan-an. 2. Ọkùnrin kan wà níbi tó ti ń wo eré ìdárayá, ó na àsíá orílẹ̀-èdè ẹ̀ sókè, ó sì ń ṣe kóríyá fáwọn olùkópa. 3. Ọmọléèwé kan ń ka ẹ̀jẹ́ orílẹ̀-èdè. 4. Ọmọ ogun kan gbé ìbọn dání. 5. Àwọn olóṣèlú méjì ń ṣe atótónu lórí ohun tí wọ́n máa ṣe fáwọn ará ìlú tí wọ́n bá dìbò fún wọn. 6. Obìnrin kan ń fi ìwé tó fi dìbò sínú àpótí ìdìbò.

      Kí làwọn nǹkan tí Kristẹni kan ò ní ṣe kó lè fi hàn pé òun ò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú nínú èrò àti ìṣe rẹ̀?

      ẸNÌ KAN LÈ BÉÈRÈ PÉ: “Kí ló dé tẹ́ ò kì í tẹrí ba fún àsíá tàbí kẹ́ ẹ kọ orin orílẹ̀-èdè?”

      • Kí lo máa sọ?

      KÓKÓ PÀTÀKÌ

      Àwọn Kristẹni máa ń sapá gan-an kí wọ́n má bàa dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú nínú èrò, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn.

      Kí lo rí kọ́?

      • Báwo ló ṣe yẹ ká máa ṣe sáwọn ìjọba èèyàn?

      • Kí nìdí táwa Kristẹni ò fi ń dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      • Àwọn nǹkan wo ló lè ṣẹlẹ̀ tó lè fẹ́ mú ká dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Ohun tó yẹ kó o ṣe

      ṢÈWÁDÌÍ

      Àwọn nǹkan tí ò rọrùn wo ló lè gba pé ká ṣe tá ò bá fẹ́ dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Jèhófà Ò Fi Wá Sílẹ̀ Rárá (3:14)

      Kí ni ìdílé lè ṣe láti múra sílẹ̀ ṣáájú fún àwọn nǹkan tó lè mú kí wọ́n dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú?

      Jẹ́ Adúróṣinṣin sí Jèhófà Tó O Bá Wà Níbi Tí Wọ́n Ti Ń Kí Àsíá (4:25)

      Kí nìdí tó fi jẹ́ pé kéèyàn máa ṣe ohun táá gbé orílẹ̀-èdè ẹ̀ ga kọ́ lohun tó ṣe pàtàkì jù téèyàn lè ṣe?

      “Ohun Gbogbo Ṣeé Ṣe fún Ọlọ́run” (5:19)

      Ka ìwé yìí kó o lè mọ bí o ò ṣe ní jẹ́ “apá kan ayé” tó o bá fẹ́ pinnu irú iṣẹ́ tí wàá ṣe.

      “Olúkúlùkù Ni Yóò Ru Ẹrù Ti Ara Rẹ̀” (Ilé Ìṣọ́, March 15, 2006)

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́