-
“Kò sí Ìkankan Lára Yín Tó Máa Ṣègb锓Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
“Inú Rere Àrà Ọ̀tọ̀” (Ìṣe 28:1-10)
18-20. Báwo làwọn ará Málítà ṣe fi “inú rere àrà ọ̀tọ̀” hàn, iṣẹ́ ìyanu wo ni Ọlọ́run sì fún Pọ́ọ̀lù lágbára láti ṣe?
18 Erékùṣù Málítà tó wà ní gúúsù Sísílì ni gbogbo àwọn tó la ìṣẹ̀lẹ̀ yìí já gúnlẹ̀ sí. (Wo àpótí náà, “Ibo Ni Málítà Wà?”) Àwọn èèyàn tó ń sọ èdè àjèjì tí wọ́n ń gbé ní erékùṣù náà fi “inú rere àrà ọ̀tọ̀” hàn sí wọn. (Ìṣe 28:2) Wọ́n dá iná fún àwọn àlejò tó gúnlẹ̀ sí èbúté yẹn kí wọ́n lè yáná, torí pé gbogbo ara wọn ló tutù tí wọ́n sì ń gbọ̀n pẹ̀pẹ̀. Iná yìí jẹ́ kí ara wọn móoru bí òjò ṣe ń rọ̀ tí òtútù sì ń mú. Yàtọ̀ síyẹn, iṣẹ́ ìyanu kan ṣẹlẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń yáná.
-