-
‘Àwọn Èèyàn Tí Ò Kàwé àti Gbáàtúù’“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
1, 2. Iṣẹ́ ìyanu wo ni Pétérù àti Jòhánù ṣe nítòsí ẹnu ilẹ̀kùn tẹ́ńpìlì?
OÒRÙN ń tàn sórí àwọn èèyàn lọ́sàn-án ọjọ́ kan. Àwọn Júù olùfọkànsìn àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn Kristi ti bẹ̀rẹ̀ sí í dé sí tẹ́ńpìlì. ‘Àkókò àdúrà’ ò sì ní pẹ́ tó.a (Ìṣe 2:46; 3:1) Pétérù àti Jòhánù gba àárín àwọn èrò rẹpẹtẹ yìí kọjá lọ sítòsí ẹnu ilẹ̀kùn tẹ́ńpìlì tí wọ́n ń pè ní Ẹlẹ́wà. Báwọn èèyàn ṣe ń sọ̀rọ̀ lọ́tùn lósì, tí ìró ẹsẹ̀ ń dún ní gbogbo àgbègbè tẹ́ńpìlì náà, bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin alágbe kan tó yarọ látìgbà tí wọ́n ti bí i ń tọrọ bárà.—Ìṣe 3:2; 4:22.
-
-
‘Àwọn Èèyàn Tí Ò Kàwé àti Gbáàtúù’“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
a Àwọn èèyàn máa ń gbàdúrà ní tẹ́ńpìlì nígbà ẹbọ àárọ̀ àti nígbà ẹbọ ìrọ̀lẹ́. “Wákàtí kẹsàn-án,” tàbí nǹkan bí aago mẹ́ta ọ̀sán ni wọ́n máa ń rú ẹbọ ìrọ̀lẹ́.
-