-
“Àwọn Àkókò Ìmúpadàbọ̀sípò” Ti Kù sí Dẹ̀dẹ̀!Ilé Ìṣọ́—2000 | September 1
-
-
IṢẸ́ yẹn kì í ṣe iṣẹ́ tí wọ́n á lè parí láàárín ọjọ́ díẹ̀, ọ̀sẹ̀ díẹ̀, tàbí oṣù díẹ̀. Àmọ́, ojú ẹsẹ̀ làwọn ọmọlẹ́yìn bẹ̀rẹ̀ sí wàásù. Bíṣẹ́ ò kúkú pẹ́ni, a kì í pẹ́ṣẹ́. Ṣùgbọ́n wọn ò mú ọkàn kúrò lórí ọ̀ràn ìmúpadàbọ̀sípò. Àpọ́sítélì Pétérù sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ nígbà tó ń bá ogunlọ́gọ̀ ńlá kan tó kóra jọ ní Jerúsálẹ́mù sọ̀rọ̀, ó wí pé: “Ẹ ronú pìwà dà, kí ẹ sì yí padà, kí a lè pa àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́, kí àwọn àsìkò títunilára lè wá láti ọ̀dọ̀ Jèhófà fúnra rẹ̀, kí ó sì lè rán Kristi tí a yàn sípò jáde fún yín, Jésù, ẹni tí ọ̀run, ní tòótọ́, gbọ́dọ̀ gbà sínú ara rẹ̀ títí di àwọn àkókò ìmúpadàbọ̀sípò ohun gbogbo èyí tí Ọlọ́run sọ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ ti ìgbà láéláé.”—Ìṣe 3:19-21.
-
-
“Àwọn Àkókò Ìmúpadàbọ̀sípò” Ti Kù sí Dẹ̀dẹ̀!Ilé Ìṣọ́—2000 | September 1
-
-
Gẹ́gẹ́ bí àpọ́sítélì Pétérù ti sọ fún ogunlọ́gọ̀ yẹn ní Jerúsálẹ́mù, ọ̀run ‘gba Jésù sínú ara rẹ̀.’ Èyí rí bẹ́ẹ̀ títí di ọdún 1914, nígbà tí Jésù gorí àlééfà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí jọba gẹ́gẹ́ bí Ọba tí Ọlọ́run yàn. Gẹ́gẹ́ bí Pétérù ti sọ tẹ́lẹ̀, ìgbà yẹn ni Jèhófà yóò “rán” Ọmọ rẹ̀ “jáde,” ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ ní ti pé Ó jẹ́ kí Jésù kó ipa tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpómúléró nínú àwọn ète Ọlọ́run. Bíbélì ṣàlàyé ìṣẹ̀lẹ̀ yìí lédè àpèjúwe, pé: “Ó [ètò àjọ Ọlọ́run lókè ọ̀run] sì bí ọmọkùnrin kan, akọ, [ìyẹn, Ìjọba Ọlọ́run ní ìkáwọ́ Jésù Kristi] ẹni tí yóò fi ọ̀pá irin ṣe olùṣọ́ àgùntàn àwọn orílẹ̀-èdè.”—Ìṣípayá 12:5.
-