-
Bánábà—“Ọmọ Ìtùnú”Ilé Ìṣọ́—1998 | April 15
-
-
Kété lẹ́yìn Pẹ́ńtíkọ́sì ọdún 33 Sànmánì Tiwa, Bánábà, tí ó jẹ́ ọmọ Léfì láti Kípírọ́sì, fínnúfíndọ̀ ta ilẹ̀ kan, ó sì kó owó rẹ̀ lé àwọn àpọ́sítélì lọ́wọ́. Èé ṣe tí ó fi ṣe ìyẹn? Àkọsílẹ̀ ìwé Ìṣe sọ fún wa pé láàárín àwọn Kristẹni ní Jerúsálẹ́mù ní àkókò náà, “wọn a pín nǹkan fún olúkúlùkù, gan-an gẹ́gẹ́ bí àìní rẹ̀ bá ṣe rí.” Ó hàn gbangba sí Bánábà pé àìní ń bẹ, ó sì fi ayọ̀ ṣe ohun kan nípa rẹ̀. (Ìṣe 4:34-37) Ó ṣeé ṣe kí ó jẹ́ ẹni tí ó rí jájẹ, ṣùgbọ́n kò lọ́ tìkọ̀ láti fi ohun ìní rẹ̀ tọrẹ, kí ó sì yọ̀ǹda ara rẹ̀ fún ìtẹ̀síwájú ire Ìjọba.b Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ náà, F. F. Bruce, wí pé: “Ibikíbi tí Bánábà bá ti rí àwọn ènìyàn tàbí ipò tí ó ń nílò ìṣírí, yóò fún wọn ní gbogbo ìṣírí tí ó bá lè fún wọn.” Èyí hàn gbangba nínú ìtàn kejì tí ó ti fara hàn.
-
-
Bánábà—“Ọmọ Ìtùnú”Ilé Ìṣọ́—1998 | April 15
-
-
b Ní ṣíṣàgbéyẹ̀wò ohun tí Òfin Mósè ti gbé kalẹ̀, àwọn kan ti béèrè bí Bánábà, ọmọ Léfì kan, ṣe wá di ẹni tí ó ní ilẹ̀. (Númérì 18:20) Ṣùgbọ́n, ó yẹ kí a kíyè sí i pé, kò ṣe kedere bóyá Palẹ́sìnì ni ilẹ̀ náà wà tàbí Kípírọ́sì. Síwájú si, ó ṣeé ṣe kí èyí wulẹ̀ jẹ́ ilẹ̀ ìsìnkú tí Bánábà ti rà ní àgbègbè Jerúsálẹ́mù. Ohun yòówù tí ì báà jẹ́, Bánábà ta ilẹ̀ rẹ̀ láti ṣèrànwọ́ fún àwọn ẹlòmíràn.
-