ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “A Gbọ́dọ̀ Ṣègbọràn sí Ọlọ́run Gẹ́gẹ́ Bí Alákòóso Dípò Èèyàn”
    “Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
    • Tọkọtaya kan ń fi Bíbélì àtàwọn ìwé tó ṣàlàyé Bíbélì wàásù fún ọkùnrin kan tó dúró síwájú ilé ẹ̀.

      Bíi tàwọn àpọ́sítélì, à ń wàásù “láti ilé dé ilé”

      16. Báwo làwọn àpọ́sítélì ṣe fi hàn pé wọ́n ti pinnu láti jẹ́rìí kúnnákúnná, báwo làwa náà sì ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ wọn?

      16 Àwọn àpọ́sítélì ò fàkókò ṣòfò rárá, ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni wọ́n pa dà sẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù. Wọ́n ń fìgboyà ‘kéde ìhìn rere nípa Kristi lójoojúmọ́ nínú tẹ́ńpìlì àti láti ilé dé ilé.’d (Ìṣe 5:42) Àwọn àpọ́sítélì náà ń fìtara wàásù, wọ́n sì ń jẹ́rìí kúnnákúnná. Kíyè sí i pé ńṣe ni wọ́n lọ ń wàásù ìhìn rere fáwọn èèyàn nínú ilé wọn bí Jésù Kristi ṣe sọ pé kí wọ́n ṣe. (Mát. 10:7, 11-14) Ó dájú pé èyí ló mú kí wọ́n lè fi ẹ̀kọ́ wọn kún Jerúsálẹ́mù. Lóde òní, ọ̀pọ̀ èèyàn ló mọ̀ pé bíi tàwọn àpọ́sítélì làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà náà ṣe ń wàásù. Bá a ṣe ń dé gbogbo ilé tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa fi hàn pé àwa náà fẹ́ ṣiṣẹ́ ìwàásù yìí kúnnákúnná, kí gbogbo èèyàn lè gbọ́ ìhìn rere. Ṣé Jèhófà sì ń bù kún iṣẹ́ ìwàásù ilé-dé-ilé tá à ń ṣe? Ó dájú pé ó ń ṣe bẹ́ẹ̀! Àìmọye èèyàn ló ti gbọ́ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, ọ̀pọ̀ lára wọn ló sì jẹ́ pé ìgbà táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà lọ wàásù nílé wọn ni wọ́n kọ́kọ́ gbọ́ ìhìn rere.

      ÌWÀÁSÙ “LÁTI ILÉ DÉ ILÉ”

      Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn pàṣẹ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn pé wọn ò gbọ́dọ̀ wàásù mọ́, wọ́n ṣì ń bá a lọ láti máa wàásù àti láti máa kọ́ni “lójoojúmọ́ nínú tẹ́ńpìlì àti láti ilé dé ilé.” (Ìṣe 5:42) Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ náà “láti ilé dé ilé?”

      Ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà katʼ oiʹkon, tá a tú sí “láti ilé dé ilé” lédè Yorùbá, tún lè túmọ̀ sí “ní ìbámu pẹ̀lú ilé.” Ọ̀pọ̀ àwọn atúmọ̀ èdè sọ pé bí wọ́n ṣe lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà ka·taʹ fi hàn pé, ńṣe làwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù wàásù láti ilé kan sí òmíì. Ọ̀rọ̀ Gíríìkì yìí kan náà ka·taʹ ni wọ́n lò nínú ìwé Lúùkù 8:1, níbi tí Lúùkù ti ròyìn pé Jésù wàásù “láti ìlú dé ìlú àti láti abúlé dé abúlé.”

      Irú ọ̀rọ̀ yìí tí wọ́n máa ń lò láti tọ́ka sí ohun tó pọ̀ ni katʼ oiʹkous. Òun ni wọ́n lò nínú Ìṣe 20:20, níbi tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ti sọ fáwọn alábòójútó pé: “Mi ò . . . fà sẹ́yìn nínú . . . kíkọ́ yín ní gbangba àti láti ilé dé ilé.” Àwọn kan sọ pé ńṣe ni ọ̀rọ̀ yìí fi hàn pé Pọ́ọ̀lù ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ nínú ilé àwọn alàgbà yẹn. Àmọ́ ẹsẹ tó tẹ̀ lé e jẹ́ ká rí i pé bọ́rọ̀ ṣe rí kọ́ nìyẹn, ó kà pé: “Àmọ́ mo jẹ́rìí kúnnákúnná fún àwọn Júù àti àwọn Gíríìkì nípa ìrònúpìwàdà sí Ọlọ́run àti ìgbàgbọ́ nínú Olúwa wa Jésù.” (Ìṣe 20:21) Ó ṣe kedere pé nígbà tí Pọ́ọ̀lù sọ pé òun ń kọ́ni láti ilé dé ilé, ohun tó ń sọ ni pé òun ń wàásù fáwọn aláìgbàgbọ́. Torí pé àwọn tí wọ́n jọ jẹ́ onígbàgbọ́ ti ronú pìwà dà, wọ́n sì ti gba Jésù gbọ́.

  • “A Gbọ́dọ̀ Ṣègbọràn sí Ọlọ́run Gẹ́gẹ́ Bí Alákòóso Dípò Èèyàn”
    “Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
    • Ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà katʼ oiʹkon, tá a tú sí “láti ilé dé ilé” lédè Yorùbá, tún lè túmọ̀ sí “ní ìbámu pẹ̀lú ilé.” Ọ̀pọ̀ àwọn atúmọ̀ èdè sọ pé bí wọ́n ṣe lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà ka·taʹ fi hàn pé, ńṣe làwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù wàásù láti ilé kan sí òmíì. Ọ̀rọ̀ Gíríìkì yìí kan náà ka·taʹ ni wọ́n lò nínú ìwé Lúùkù 8:1, níbi tí Lúùkù ti ròyìn pé Jésù wàásù “láti ìlú dé ìlú àti láti abúlé dé abúlé.”

      Irú ọ̀rọ̀ yìí tí wọ́n máa ń lò láti tọ́ka sí ohun tó pọ̀ ni katʼ oiʹkous. Òun ni wọ́n lò nínú Ìṣe 20:20, níbi tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ti sọ fáwọn alábòójútó pé: “Mi ò . . . fà sẹ́yìn nínú . . . kíkọ́ yín ní gbangba àti láti ilé dé ilé.” Àwọn kan sọ pé ńṣe ni ọ̀rọ̀ yìí fi hàn pé Pọ́ọ̀lù ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ nínú ilé àwọn alàgbà yẹn. Àmọ́ ẹsẹ tó tẹ̀ lé e jẹ́ ká rí i pé bọ́rọ̀ ṣe rí kọ́ nìyẹn, ó kà pé: “Àmọ́ mo jẹ́rìí kúnnákúnná fún àwọn Júù àti àwọn Gíríìkì nípa ìrònúpìwàdà sí Ọlọ́run àti ìgbàgbọ́ nínú Olúwa wa Jésù.” (Ìṣe 20:21) Ó ṣe kedere pé nígbà tí Pọ́ọ̀lù sọ pé òun ń kọ́ni láti ilé dé ilé, ohun tó ń sọ ni pé òun ń wàásù fáwọn aláìgbàgbọ́. Torí pé àwọn tí wọ́n jọ jẹ́ onígbàgbọ́ ti ronú pìwà dà, wọ́n sì ti gba Jésù gbọ́.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́