-
Fílípì Batisí Ìjòyè Òṣìṣẹ́ Ará Etiópíà kanIlé-Ìṣọ́nà—1996 | July 15
-
-
BÍ Ó ti ń lọ lórí kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ̀, ará Etiópíà kan ń fi ọgbọ́n lo àkókò rẹ̀. Ó ń kàwé sókè—àṣà tí ó wọ́pọ̀ láàárín àwọn arìnrìn àjò ọ̀rúndún kìíní. Ọkùnrin tí a ń sọ yìí jẹ́ ìjòyè òṣìṣẹ́ “tí ó wà ní ipò agbára lábẹ́ Káńdésì ọbabìnrin àwọn ará Etiópíà.”a Ó “ń bójú tó gbogbo ìṣúra rẹ̀”—ìyẹn ni pé, ó jẹ́ mínísítà ìnáwó. Ìjòyè òṣìṣẹ́ yìí ń kà láti inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kí ó ba lè jèrè ìmọ̀.—Ìṣe 8:27, 28.
-
-
Fílípì Batisí Ìjòyè Òṣìṣẹ́ Ará Etiópíà kanIlé-Ìṣọ́nà—1996 | July 15
-
-
a “Káńdésì” kì í ṣe orúkọ ṣùgbọ́n oyè (ó fara jọ “Fáráò” àti “Késárì”) tí a lò fún àwọn ọbabìnrin Etiópíà tí wọ́n jẹ tẹ̀ léra.
-
-
Fílípì Batisí Ìjòyè Òṣìṣẹ́ Ará Etiópíà kanIlé-Ìṣọ́nà—1996 | July 15
-
-
Èé Ṣe Tí A Fi Pè É Ní Ìwẹ̀fà?
Jálẹ̀ ìròyìn Ìṣe orí 8, a tọ́ka sí ará Etiópíà náà gẹ́gẹ́ bí “ìwẹ̀fà.” Bí ó ti wù kí ó rí, níwọ̀n bí Òfin Mósè kò ti fàyè gba ọkùnrin tí a ti tẹ̀ lọ́dàá láti wá sínú ìjọ, ó dájú pé ọkùnrin yìí kì í ṣe ìwẹ̀fà ní ti gidi. (Diutarónómì 23:1) Ọ̀rọ̀ Gíríìkì fún “ìwẹ̀fà” lè tọ́ka sí ẹnì kan tí ó wà ní ipò gíga. Nípa báyìí, ará Etiópíà náà jẹ́ ìjòyè òṣìṣẹ́ lábẹ́ ọbabìnrin Etiópíà.
-