-
Ìjọ “Wọnú Àkókò Àlàáfíà”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
1, 2. Kí ni Sọ́ọ̀lù fẹ́ lọ ṣe ní Damásíkù?
ÀWỌN arìnrìn àjò náà ti ń sún mọ́ Damásíkù, níbi tí wọ́n ti fẹ́ lọ ṣiṣẹ́ ibi tó wà lọ́kàn wọn. Wọ́n fẹ́ lọ fipá mú àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù tí wọ́n kórìíra nínú ilé wọn, kí wọ́n dè wọ́n, kí wọ́n dójú tì wọ́n, kí wọ́n sì wọ́ wọn lọ sọ́dọ̀ ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn ní Jerúsálẹ́mù, kí wọ́n lè fìyà jẹ wọ́n.
2 Sọ́ọ̀lù tó jẹ́ aṣáájú wọn ti lọ́wọ́ sí ikú ẹnì kan tẹ́lẹ̀.a Kò tíì pẹ́ sígbà yẹn táwọn agbawèrèmẹ́sìn bíi tiẹ̀ sọ Sítéfánù tó jẹ́ olóòótọ́ ọmọ ẹ̀yìn Jésù lókùúta pa níṣojú ẹ̀. (Ìṣe 7:57–8:1) Síbẹ̀, inú ṣì ń bí i sáwọn ọmọlẹ́yìn Jésù tó ń gbé ní Jerúsálẹ́mù, Sọ́ọ̀lù wá sọ ara rẹ̀ di irinṣẹ́ Èṣù láti tan inúnibíni kálẹ̀. Ó fẹ́ pa ẹ̀sìn tó kà sí eléwu, tí wọ́n ń pè ní “Ọ̀nà Náà” run.—Ìṣe 9:1, 2; wo àpótí náà, “Sọ́ọ̀lù Gbàṣẹ Láti Lọ Mú Àwọn Kristẹni ní Damásíkù.”
-