-
Ìjọ “Wọnú Àkókò Àlàáfíà”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
12 Tọkàntọkàn ni Ananáyà fi gbà láti ṣe iṣẹ́ tí Jésù gbé fún un, Jèhófà sì bù kún un. Ṣéwọ náà máa ń ṣègbọràn sí àṣẹ tó sọ pé ká máa jẹ́rìí kúnnákúnná, tí ò bá tiẹ̀ rọrùn láti máa ṣe bẹ́ẹ̀? Bí àpẹẹrẹ, ó lè má rọrùn fáwọn kan láti wàásù fún ẹni tí wọn ò mọ̀ rí, ẹ̀rù sì lè máa bà wọ́n tí wọ́n bá ń wàásù láti ilé dé ilé. Kì í rọrùn fáwọn míì láti wàásù fáwọn èèyàn níbi iṣẹ́, ní òpópónà, lórí tẹlifóònù tàbí nípasẹ̀ lẹ́tà. Ananáyà borí ẹ̀rù tó ń bà á, torí náà ó ran Sọ́ọ̀lù lọ́wọ́ láti rí ẹ̀mí mímọ́ gbà.b Ó ṣàṣeyọrí torí pé ó gbẹ́kẹ̀ lé Jésù, ó sì gbà pé Sọ́ọ̀lù lè di arákùnrin òun. Bíi ti Ananáyà, àwa náà lè borí ẹ̀rù tó ń bà wá, tá a bá gbà pé Jésù ló ń darí iṣẹ́ ìwàásù, tá à ń fọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ro ara wa wò, tá a sì gbà pé àwọn tó burú gan-an ṣì lè di Kristẹni.—Mát. 9:36.
-
-
Ìjọ “Wọnú Àkókò Àlàáfíà”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
b Àwọn àpọ́sítélì ni Ọlọ́run sábà máa ń lò láti fún àwọn èèyàn ní ẹ̀bùn ẹ̀mí mímọ́. Àmọ́ nínú ọ̀rọ̀ tó ṣàrà ọ̀tọ̀ yìí, ó jọ pé Jésù fún Ananáyà láṣẹ láti fún Sọ́ọ̀lù ní ẹ̀mí mímọ́. Lẹ́yìn tí Sọ́ọ̀lù di Kristẹni, ó pẹ́ díẹ̀ kó tó láǹfààní láti rí àwọn àpọ́sítélì méjìlá náà. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ó jọ pé ó ti bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù ní gbogbo àkókò yẹn. Torí náà, Jésù rí i dájú pé Sọ́ọ̀lù ní okun tó tó láti máa bá iṣẹ́ ìwàásù tó gbé lé e lọ́wọ́ nìṣó.
-