-
Ápólò—Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ Olùpòkìkí Òtítọ́ KristẹniIlé-Ìṣọ́nà—1996 | October 1
-
-
Ìṣarasíhùwà oníwọ̀ntúnwọ̀nsì kan náà ti Ápólò tún fara hàn nínú ìmúratán rẹ̀ láti gba lẹ́tà ìdámọ̀ràn láti ọwọ́ àwọn ará ní Éfésù lọ sí ìjọ tí ó wà ní Kọ́ríńtì. Ìròyìn náà ń bá a nìṣó pé: “Síwájú sí i, nítorí pé ó ní ìfẹ́ ọkàn láti sọdá lọ sí Ákáyà, àwọn ará kọ̀wé sí àwọn ọmọ ẹ̀yìn, ní gbígbà wọ́n níyànjú láti fi inú rere gbà á.” (Ìṣe 18:27; 19:1) Ápólò kò béèrè pé kí a tẹ́wọ́ gba òun nítorí ànímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fi ìwọ̀ntúnwọ̀nsì tẹ̀ lé ètò tí ìjọ Kristẹni ṣe.
-
-
Ápólò—Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ Olùpòkìkí Òtítọ́ KristẹniIlé-Ìṣọ́nà—1996 | October 1
-
-
Àbájáde iṣẹ́ òjíṣẹ́ Ápólò ní Kọ́ríńtì ní ìbẹ̀rẹ̀ tayọ lọ́lá. Ìwé Ìṣe ròyìn pé: “Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó ṣe ìrànlọ́wọ́ ńláǹlà fún àwọn wọnnì tí wọ́n ti gbà gbọ́ ní tìtorí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run; nítorí pé pẹ̀lú ìgbóná janjan ni ó fi hàn kínníkínní ní gbangba pé àwọn Júù kò tọ̀nà, nígbà tí ó fi hàn gbangba nípasẹ̀ Ìwé Mímọ́ pé Jésù ni Kristi náà.”—Ìṣe 18:27, 28.
Ápólò fara rẹ̀ jìn fún iṣẹ́ ìsìn ìjọ, ní fífún àwọn ará níṣìírí nípasẹ̀ ìmúrasílẹ̀ àti ìtara rẹ̀. Kí ni kọ́kọ́rọ́ sí àṣeyọrí rẹ̀? Dájúdájú, Ápólò ní agbára àdánidá, ó sì lo ìgboyà nínú jíjiyàn pẹ̀lú àwọn Júù ní gbangba fún ìgbà pípẹ́. Ṣùgbọ́n ní pàtàkì jù, ó jíròrò ní lílo Ìwé Mímọ́.
-