-
Jòhánù Arinibọmi Ṣètò Ọ̀nà Sílẹ̀Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Ọ̀rọ̀ Jòhánù máa ń wú àwọn tó ń fetí sí i lórí. Ọ̀pọ̀ nínú wọn sì rí i pé ó yẹ káwọn ronú pìwà dà, ìyẹn ni pé, kí wọ́n yí ìwà àti ìṣe wọn pa dà, kí wọ́n sì yẹra fáwọn ohun tí ò dáa tí wọ́n ń ṣe tẹ́lẹ̀. “Jerúsálẹ́mù àti gbogbo Jùdíà àti gbogbo ìgbèríko tó yí Jọ́dánì ká” làwọn èèyàn ti ń wá sọ́dọ̀ rẹ̀. (Mátíù 3:5) Ọ̀pọ̀ àwọn tó wá bá Jòhánù ló ronú pìwà dà. Jòhánù á wá rì wọ́n bọmi nínú Odò Jọ́dánì. Kí nìdí tó fi ń ṣe bẹ́ẹ̀?
Ó ń ri àwọn èèyàn bọmi láti fi hàn pé wọ́n ti ronú pìwà dà tọkàntọkàn lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n dá lòdì sí Òfin Mósè. (Ìṣe 19:4) Àmọ́ kì í ṣe gbogbo àwọn tó ń wá sọ́dọ̀ rẹ̀ ló ronú pìwà dà tọkàntọkàn. Nígbà tí àwọn aṣáájú ẹ̀sìn kan, ìyẹn àwọn Farisí àtàwọn Sadusí wá bá a, Jòhánù pè wọ́n ní “ọmọ paramọ́lẹ̀.” Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ so èso tó yẹ ìrònúpìwàdà. Ẹ má ṣe dá ara yín lójú, kí ẹ sì sọ fún ara yín pé, ‘A ní Ábúráhámù ní baba.’ Torí mò ń sọ fún yín pé Ọlọ́run lè gbé àwọn ọmọ dìde fún Ábúráhámù látinú àwọn òkúta yìí. Àáké ti wà níbi gbòǹgbò àwọn igi báyìí. Torí náà, gbogbo igi tí kò bá so èso tó dáa la máa gé lulẹ̀, tí a sì máa jù sínú iná.”—Mátíù 3:7-10.
-
-
Jòhánù Arinibọmi Ṣètò Ọ̀nà Sílẹ̀Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Torí náà, ó ṣe kedere pé bí Jòhánù ṣe ń kéde fáwọn èèyàn pé kí wọ́n “ronú pìwà dà, torí Ìjọba ọ̀run ti sún mọ́lé” bọ́ sákòókò gan-an. (Mátíù 3:2) Ṣe ló ń jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ̀ pé Jésù Kristi, Ọba tí Jèhófà yàn, máa tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀.
-