ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́—2003 | September 1
    • Kí Nìdí Tí Jèhófà Fi Fàyè Gba Ìjìyà?

      10, 11. (a) Gẹ́gẹ́ bí Róòmù 8:19-22 ṣe sọ, kí ló ṣẹlẹ̀ sí “gbogbo ìṣẹ̀dá”? (b) Báwo la ṣe lè mọ ẹni tó tẹ ìṣẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo?

      10 Apá kan lára lẹ́tà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ sáwọn ará Róòmù túbọ̀ tànmọ́lẹ̀ sórí kókó pàtàkì yìí. Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “Ìfojúsọ́nà oníhàáragàgà ìṣẹ̀dá ń dúró de ìṣípayá àwọn ọmọ Ọlọ́run. Nítorí a tẹ ìṣẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo, kì í ṣe nípasẹ̀ ìfẹ́ òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹni tí ó tẹ̀ ẹ́ lórí ba, nítorí ìrètí pé a óò dá ìṣẹ̀dá tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìsọdẹrú fún ìdíbàjẹ́, yóò sì ní òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run. Nítorí àwa mọ̀ pé gbogbo ìṣẹ̀dá ń bá a nìṣó ní kíkérora pa pọ̀ àti ní wíwà nínú ìrora pa pọ̀ títí di ìsinsìnyí.”—Róòmù 8:19-22.

      11 Tá a bá fẹ́ lóye àwọn ẹsẹ wọ̀nyí, a gbọ́dọ̀ kọ́kọ́ dáhùn àwọn ìbéèrè pàtàkì kan. Bí àpẹẹrẹ, Ta ló tẹ ìṣẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo? Àwọn kan sọ pé Sátánì ni; àwọn mìíràn sì sọ pé Ádámù ni. Àmọ́ kò lè jẹ́ èyíkéyìí lára àwọn méjèèjì. Kí nìdí? Ìdí ni pé ẹni náà tó tẹ ìṣẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo ṣe bẹ́ẹ̀ ó sì tún fúnni ní “ìrètí.” Dájúdájú, ó fún wa nírètí pé bópẹ́ bóyá ‘a óò dá àwọn olóòótọ́ sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìsọdẹrú fún ìdíbàjẹ́.’ Ádámù tàbí Sátánì kò lè fúnni nírú ìrètí yìí. Jèhófà nìkan ló lè ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí náà, ó ti wá ṣe kedere báyìí pé òun ló tẹ ìṣẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo.

      12. Irú ìbéèrè wo ló ti dìde nípa ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ náà “gbogbo ìṣẹ̀dá,” báwo la sì ṣe lè dáhùn ìbéèrè náà?

      12 Àmọ́ o, kí ni “gbogbo ìṣẹ̀dá” tá a mẹ́nu bà nínú ẹsẹ Bíbélì yìí? Àwọn kan sọ pé “gbogbo ìṣẹ̀dá” túmọ̀ sí gbogbo nǹkan tó wà láyé títí kan àwọn ẹranko àti ewéko. Àmọ́, ǹjẹ́ àwọn ẹranko àtàwọn ewéko ní ìrètí láti ní “òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run”? Rárá o. (2 Pétérù 2:12) Nígbà náà, àwọn ẹ̀dá èèyàn nìkan ni gbólóhùn náà “gbogbo ìṣẹ̀dá” lè túmọ̀ sí. Ìṣẹ̀dá yìí ni ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú ń hàn léèmọ̀ nítorí ọ̀tẹ̀ tó wáyé ní ọgbà Édẹ́nì, ó sì wá nílò ìrètí gan-an báyìí.—Róòmù 5:12.

      13. Ipa wo ni ọ̀tẹ̀ tó wáyé ní Édẹ́nì ní lórí ẹ̀dá èèyàn?

      13 Ọṣẹ́ wo gan-an ni ọ̀tẹ̀ náà ti ṣe fún ẹ̀dá ènìyàn? Ọ̀rọ̀ kan ṣoṣo ni Pọ́ọ̀lù fi pe àbájáde rẹ̀, ọ̀rọ̀ náà ni: ìmúlẹ̀mófo.a Gẹ́gẹ́ bí ìwé kan tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ ti sọ, ọ̀rọ̀ yìí ṣàpèjúwe “bó ṣe jẹ́ àṣedànù bí irin iṣẹ́ kan kò bá lè ṣe iṣẹ́ tá a ṣe é fún.” A dá èèyàn láti wà láàyè títí láé, kí wọ́n máa ṣiṣẹ́ pa pọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdílé kan tó pé, tó wà níṣọ̀kan, kí wọ́n sì máa bojú tó ilẹ̀ ayé tó jẹ́ ọgbà ẹlẹ́wà. Àmọ́ dípò èyí, ẹ̀mí wọn kì í gùn, ìrora ni ṣáá, ìgbésí ayé wọn sì kún fún ìṣòro. Ńṣe ló rí gẹ́gẹ́ bí Jóòbù ṣe sọ ọ́ pé: “ènìyàn, tí obìnrin bí, ọlọ́jọ́ kúkúrú ni, ó sì kún fún ṣìbáṣìbo.” (Jóòbù 14:1) Áà, ìmúlẹ̀mófo gbáà ni lóòótọ́!

      14, 15. (a) Ẹ̀rí wo ló fi hàn pé ìdájọ́ tí Jèhófà ṣe fún ẹ̀dá èèyàn bẹ́tọ̀ọ́ mu? (b) Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi sọ pé ‘kì í ṣe nípasẹ̀ ìfẹ́ ìṣẹ̀dá fúnra rẹ̀’ la fi tẹ̀ ẹ́ lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo?

      14 A ti wá débi ìbéèrè tó ṣe kókó jù lọ wàyí, ìbéèrè náà ni: Kí nìdí tí “Onídàájọ́ gbogbo ilẹ̀ ayé” fi tẹ ẹ̀dá lórí ba báyìí tí ìgbésí ayé wọn sì kún fún ìrora? (Jẹ́nẹ́sísì 18:25) Ṣé ohun tó tọ́ ló ṣe yìí? Ó dára, rántí ohun táwọn òbí wa àkọ́kọ́ ṣe. Nípa ṣíṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run, ńṣe ni wọ́n lẹ̀dí àpò pọ̀ pẹ̀lú Sátánì, ẹni tó fàáké kọ́rí pé Jèhófà kò lẹ́tọ̀ọ́ láti jẹ́ ọba aláṣẹ. Nípa ìwà wọn, wọ́n ti èrò náà lẹ́yìn pé ìgbésí ayé ẹ̀dá èèyàn á lójú láìfi ti Jèhófà ṣe, kí ẹ̀dá ẹ̀mí kan tó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sì máa darí wọn. Ohun táwọn ọlọ̀tẹ̀ yìí ń fẹ́ ni Jèhófà fún wọn ní ti bó ṣe fìyà jẹ wọ́n. Ó gba ẹ̀dá èèyàn láyè láti ṣàkóso ara rẹ̀ lábẹ́ ìdarí Sátánì. Nínú irú ipò báwọ̀nyí, ìpinnu wo ló tún lè dára ju títẹ̀ tí Ọlọ́run tẹ ẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo lọ, àmọ́ to wá fún wọn nírètí?

      15 Lóòótọ́, kì í ṣe ‘nípasẹ̀ ìfẹ́ ìṣẹ̀dá fúnra rẹ̀’ lèyí fi ṣẹlẹ̀ o. Ńṣe la bí wa gẹ́gẹ́ bí ẹrú fún ẹ̀ṣẹ̀ àti ìdíbàjẹ́ láìsí ohunkóhun tá a lè ṣe sí i. Àmọ́ nínú àánú Jèhófà, ó jẹ́ kí Ádámù àti Éfà lo ọdún tó ṣẹ́ kù nínú ìgbésí ayé wọn kí wọ́n sì bímọ. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti tẹ àwa tá a jẹ́ àtọmọdọ́mọ wọn lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú, a láǹfààní láti ṣe ohun tí Ádámù àti Éfà kùnà láti ṣe. A lè fetí sí Jèhófà ká sì kẹ́kọ̀ọ́ pé jíjẹ́ tó jẹ́ ọba aláṣẹ bẹ́tọ̀ọ́ mu, pé kìkì ohun tí ìṣàkóso èèyàn láìfi ti Jèhófà ṣe máa ń mú wá ni ìrora, ìjákulẹ̀ àti ìmúlẹ̀mófo. (Jeremáyà 10:23; Ìṣípayá 4:11) Ńṣe ni ìṣàkóso Sátánì sì tún máa ń mú kí ọ̀ràn náà túbọ̀ burú sí i. Ìtàn ẹ̀dá èèyàn jẹ́rìí sí i pé òtítọ́ lèyí.—Oníwàásù 8:9.

      16. (a) Kí nìdí tó fi lè dá wa lójú pé Jèhófà kọ́ ló ń fa ìjìyà tó wà láyé lónìí? (b) Ìrètí wo ni Jèhófà ti fún àwọn èèyàn tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́?

      16 Ó wá hàn kedere báyìí pé ohun tó tọ́ ni Jèhófà ṣe bó ṣe tẹ ẹ̀dá èèyàn lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo. Àmọ́, ǹjẹ́ èyí wá túmọ̀ sí pé Jèhófà ló ń fa ìmúlẹ̀mófo àti ìjìyà tó ń han ẹnì kọ̀ọ̀kan wa léèmọ̀ lónìí? Ó dára, ronú nípa adájọ́ kan tó ṣèdájọ́ tó tọ́ tó sì yẹ fún ọ̀daràn kan. Ọ̀daràn náà lè jìyà gan-an nígbà tó bá ń ṣẹ̀wọ̀n, àmọ́ ṣé ó lè wá máa dá adájọ́ náà lẹ́bi pé òun ló fa ìjìyà fún òun? Kò le ṣe bẹ́ẹ̀! Dájúdájú, Jèhófà kọ́ ló ń fa ìwà ibi. Jákọ́bù 1:13 sọ pé: “A kò lè fi àwọn ohun tí ó jẹ́ ibi dán Ọlọ́run wò, bẹ́ẹ̀ ni òun fúnra rẹ̀ kì í dán ẹnikẹ́ni wò.” Ẹ jẹ́ ká tún rántí pé Jèhófà ṣe ìdájọ́ yìí ‘pẹ̀lú ìrètí.’ Ó ti ṣètò tìfẹ́tìfẹ́ fún ìrandíran Ádámù àti Éfà tí wọ́n bá jẹ́ olóòótọ́ láti rí òpin ìmúlẹ̀mófo náà kí wọ́n lè máa yọ̀ nítorí “òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run.” Títí ayérayé, ẹ̀rù ò tún ní máa ba ẹ̀dá èèyàn olóòótọ́ mọ́ pé a tún máa tẹ ẹ̀dá lórí ba fún ìmúlẹ̀mófo tó ń kó ìrora bá wọn. Ọ̀nà tó tọ́ tó sì yẹ tí Jèhófà gbà bójú tó ọ̀ràn náà yóò ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí ayé pé jíjẹ́ tó jẹ́ ọba aláṣẹ bẹ́tọ̀ọ́ mu.—Aísáyà 25:8.

  • Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́—2003 | September 1
    • a Ọ̀rọ̀ Gíríìkì kan náà tí Pọ́ọ̀lù lò fún “ìmúlẹ̀mófo” ni wọ́n lò nínú Bíbélì Gíríìkì ti ìtumọ̀ Septuagint láti fi túmọ̀ ọ̀rọ̀ kan tí Sólómọ́nì lò léraléra nínú ìwé Oníwàásù, ọ̀rọ̀ náà sì ni “asán ni gbogbo rẹ̀!”—Oníwàásù 1:2, 14; 2:11, 17; 3:19; 12:8.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́