ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìṣẹ̀dá Ń Fi Ọgbọ́n Ọlọ́run Hàn
    Ilé Ìṣọ́—2008 | May 1
    • Ìṣẹ̀dá Ń Fi Ọgbọ́n Ọlọ́run Hàn

      “Òun ni Ẹni tí ń kọ́ wa ju àwọn ẹranko ilẹ̀ ayé, ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹ̀dá tí ń fò lójú ọ̀run pàápàá.”—JÓÒBÙ 35:11.

      ORÍṢIRÍṢI àrà làwọn ẹyẹ máa ń dá. Bí wọ́n ṣe máa ń dárà lójú ọ̀run máa ń jọ àwọn tó ṣe ọkọ̀ òfuurufú lójú gan-an. Àwọn ẹyẹ kan máa ń fo ẹgbẹẹgbẹ̀rún kìlómítà lórí agbami òkun láìsí ohun tó máa fi wọ́n mọ̀nà, wọ́n á sì dé ibi tí wọ́n ń lọ láìṣìnà.

      Àrà mìíràn tó ta yọ táwọn ẹyẹ tún máa ń dá tó fi hàn pé ọlọ́gbọ́n ni Ẹni tó dá wọn ni pé, wọ́n mọ bí wọ́n ṣe lè fi ìró àti orin bára wọn sọ̀rọ̀. Ẹ jẹ́ ká gbé àwọn àpẹẹrẹ díẹ̀ yẹ̀ wò.

      Àwọn Ẹyẹ Máa Ń Bára Wọn Sọ̀rọ̀

      Oríṣi àwọn ẹyẹ kan máa ń bára wọn sọ̀rọ̀ kí wọ́n tó jáde nínú ilé ẹyin. Bí àpẹẹrẹ, ó kéré tán, abo àparò máa ń yé ẹyin tó mẹ́jọ, ẹyin kan ló sì ń yé lóòjọ́. Bí ọmọ tó wà nínú ẹyin kọ̀ọ̀kan bá dàgbà bó ṣe yẹ, á jẹ́ pé ọjọ́ mẹ́jọ ló máa gbà kí gbogbo wọn tó jáde tán nínú ilé ẹyin wọn. Yóò wá di pé kí ìyá àwọn ọmọ ẹyẹ náà gba iṣẹ́ títọ́jú àwọn tó ti jáde nínú ẹyin wọn nígbà tí àwọn ọmọ yòókù kò tíì jáde. Àmọ́, dípò ìyẹn, ohun tó máa ń ṣẹlẹ̀ ni pé gbogbo ẹyin mẹ́jẹ̀ẹ̀jọ náà ló ń pamọ sọ́wọ́ kan náà láàárín wákàtí mẹ́fà. Kí ló mú kí èyí ṣeé ṣe? Ìdí pàtàkì kan táwọn aṣèwádìí sọ pé ó fà á ni pé àwọn ọmọ ẹyẹ àparò tó wà nínú ilé ẹyin máa ń ta ara wọn lólobó, tí wọ́n á sì tipa bẹ́ẹ̀ ṣètò láti jáde kúrò nínú ilé ẹyin wọn lákòókò tó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ ìgbà kan náà.

      Nígbà táwọn ẹyẹ bá dàgbà, àwọn akọ ló sábà máa ń kọrin. Wọ́n máa ń ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí wọ́n bá fẹ́ gùn, kí wọ́n bàa lè fàmì sí ibi tí wọ́n máa ń jẹ̀ dé, tàbí láti fa abo mọ́ra. Ẹgbẹẹgbẹ̀rún ẹyẹ ló wà lóríṣiríṣi, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ló sì ní ìró tirẹ̀. Èyí ló máa ń jẹ́ káwọn abo mọ àwọn akọ tó jẹ́ irú tiwọn.

      Òwúrọ̀ kùtùkùtù àti ìrọ̀lẹ́ làwọn ẹyẹ sábà máa ń kọrin, ó sì nídìí tó fi jẹ́ pé àkókò yẹn ni wọ́n ń kọrin. Ìdí náà ni pé afẹ́fẹ́ àti ariwo tó lè di orin ẹyẹ lọ́wọ́ kì í fi bẹ́ẹ̀ pọ̀ lákòókò yẹn. Àwọn aṣèwádìí ti wá rí i pé òwúrọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ làwọn ẹyẹ máa ń kọrin dáadáa ju ti ọ̀sán lọ.

      Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn akọ ẹyẹ ló sábà máa ń kọrin, àti akọ àti abo ló ní oríṣiríṣi ìró tó ní ìtumọ̀ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Bí àpẹẹrẹ, irú àwọn ẹyẹ ìbákà kan ní ìró ohùn mẹ́sàn-án tó yàtọ̀ síra wọn. Ìró kan wà fún ṣíṣe ìkìlọ̀ nípa ewu tó wà lójú ọ̀run, irú bí ìgbà tí ẹyẹ apẹyẹjẹ bá ń fò kiri, ó tún ní ìró mìíràn tó fi ń ṣèkìlọ̀ nígbà tí ewu bá wà lórí ilẹ̀.

      Ẹ̀bùn Tó Dára Jù Lọ

      Ọgbọ́n tí Ọlọ́run dá mọ́ àwọn ẹyẹ wúni lórí gan-an ni. Àmọ́ tó bá kan ti ọ̀rọ̀ sísọ, àwa èèyàn ló ta yọ. Jóòbù 35:11 sọ pé, Ọlọ́run dá àwa èèyàn lọ́nà tá a fi “gbọ́n ju àwọn ẹ̀dá tí ń fò lójú ọ̀run pàápàá.” Ohun tó ṣàrà ọ̀tọ̀ nípa àwa èèyàn ni pé a lè fi ohùn wa ṣàlàyé nǹkan tó díjú kó sì yéni yékéyéké, a sì tún máa ń fara ṣàpèjúwe nǹkan.

      Ó jọ pé Ọlọ́run ti dá a mọ́ àwọn ọmọdé láti kọ́ àwọn èdè tó díjú, kò sì sí ẹ̀dá abẹ̀mí mìíràn tó nírú ẹ̀bùn yìí. Ìwé ìròyìn kan tó wà lórí íńtánẹ́ẹ̀tì, tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ American Scientist sọ pé: “Àwọn ọmọ àfànítẹ̀tẹ́ máa ń kọ́ èdè báwọn òbí wọn ò bá tiẹ̀ bá wọn sọ ọ́ ní tààràtà; àwọn ọmọ tí wọ́n jẹ́ adití tiẹ̀ máa ń hùmọ̀ èdè adití tiwọn fúnra wọn bí wọn ò bá tiẹ̀ kọ́ wọn ní èdè adití nílé wọn.”

  • Ìṣẹ̀dá Ń Fi Ọgbọ́n Ọlọ́run Hàn
    Ilé Ìṣọ́—2008 | May 1
    • Ẹ̀kọ́ Wo Lo Rí Kọ́?

      Ẹ̀kọ́ wo lo rí kọ́ nígbà tó o bá ń gbọ́ orin dídùn yùngbà táwọn ẹyẹ ń kọ? Tàbí tó o bá ń gbọ́ tí ọmọ kékeré kan ṣẹ̀ṣẹ̀ ń kọ́ bá a ṣe ń sọ̀rọ̀? Ǹjẹ́ o rí ọgbọ́n Ọlọ́run nínú àwọn ohun tó dá wọ̀nyí?

      Lẹ́yìn tí Dáfídì tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn tó kọ Sáàmù ti ṣàṣàrò lórí ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà dá òun, ó sọ látọkàn wá fún Ọlọ́run pé: “Èmi yóò gbé ọ lárugẹ, nítorí pé lọ́nà amúnikún-fún-ẹ̀rù ni a ṣẹ̀dá mi tìyanu-tìyanu. Àgbàyanu ni àwọn iṣẹ́ rẹ, bí ọkàn mi ti mọ̀ dáadáa.” (Sáàmù 139:14) Bó o ṣe ń mọrírì àwọn ìṣẹ̀dá Ọlọ́run tó o sì ń ronú nípa bí wọ́n ṣe ń fi ọgbọ́n Ọlọ́run hàn, ó dájú pé ìgbàgbọ́ tó o ní pé Ọlọ́run á máa tọ́ ẹ sọ́nà yóò túbọ̀ máa lágbára sí i.

  • Àwọn Ìràwọ̀ Ń Fi Agbára Ọlọ́run Hàn
    Ilé Ìṣọ́—2008 | May 1
    • Àwọn Ìràwọ̀ Ń Fi Agbára Ọlọ́run Hàn

      “Ẹ gbé ojú yín sókè réré, kí ẹ sì wò. Ta ni ó dá nǹkan wọ̀nyí? Ẹni tí ń mú ẹgbẹ́ ọmọ ogun wọn jáde wá ni, àní ní iye-iye, àwọn tí ó jẹ́ pé àní orúkọ ni ó fi ń pe gbogbo wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ yanturu okun rẹ̀ alágbára gíga, àti ní ti pé òun ní okun inú nínú agbára, kò sí ìkankan nínú wọn tí ó dàwáàrí.”—AÍSÁYÀ 40:26.

      OÒRÙN jẹ́ oríṣi ìràwọ̀ kan tó tóbi, àmọ́ àwọn ìràwọ̀ mìíràn wà tó tún tóbi ju oòrùn lọ. Síbẹ̀ náà, oòrùn tóbi ju ayé lọ ní ìlọ́po ọ̀kẹ́ mẹ́rìndínlógún àtààbọ̀ [330,000]. Èyí tó pọ̀ jù lára àwọn ìràwọ̀ tó sún mọ́ ayé ni kò tóbi tó oòrùn. Àmọ́ ṣá o, àwọn ìràwọ̀ míì bíi èyí tí wọ́n ń pè ní V382 Cygni tóbi ju oòrùn lọ ní ìlọ́po mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n.

      Báwo ni agbára tó ń jáde láti ara oòrùn ṣe pọ̀ tó? Wo bí iná kan ti ní láti lágbára tó bó o bá fi kìlómítà mẹ́ẹ̀ẹ́dógún jìnnà sí i, àmọ́ tó ṣì ń rà ọ́ lára burúkú-burúkú. Nǹkan bí àádọ́jọ mílíọ̀nù [150,000,000] kìlómítà ni oòrùn fi jìnnà sí ayé. Síbẹ̀ lọ́jọ́ tí oòrùn bá mú dáadáa, ìwọ̀n bó ṣe gbóná tó lè ta èèyàn lára gan-an! Ṣíún báyìí lára agbára oòrùn ló ń dé sí ayé, síbẹ̀ ìwọ̀nba díẹ̀ yìí ti tó láti gbé ẹ̀mí àwọn ohun alààyè ró lórí ilẹ̀ ayé.

      Kódà, àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì ti ṣírò rẹ̀ pé àpapọ̀ agbára tó ń jáde lára oòrùn nìkan ti tó láti gbé ẹ̀mí àwọn ohun alààyè ró nínú ọ̀kẹ́ àìmọye irú ayé wa yìí. Tún wo ọ̀nà míì tá a lè gbà mọ bí agbára oòrùn ṣe tó. Ilé iṣẹ́ tó ń sọ ìròyìn nípa ojú ọjọ́ nílẹ̀ Amẹ́ríkà sọ pé, tá a bá tọ́jú agbára tó ń jáde lára oòrùn pa mọ́ ní ìṣẹ́jú àáyá kan péré, “iye agbára yẹn á tó agbára iná mànàmáná” tí orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà máa lò ní “mílíọ̀nù mẹ́sàn-án ọdún.”

      Ohun kan wà nínú oòrùn tó máa ń mú kí agbára tó kàmàmà jáde. Oòrùn tóbi gan-an ni, agbára tó sì ń ti inú rẹ̀ wá pọ̀ débi pé yóò gba àìmọye mílíọ̀nù ọdún kí agbára tó ń jáde bọ náà tó lè dé ìta. Ilé iṣẹ́ tó ń sọ ìròyìn nípa ojú ọjọ́ nílẹ̀ Amẹ́ríkà sọ nínú ìkànnì orí Íńtánẹ́ẹ̀tì wọn pé: “Bó bá ṣẹlẹ̀ pé oòrùn ṣíwọ́ agbára tó ń mú jáde lónìí yìí, yóò tó àádọ́ta mílíọ́nù ọdún ká tó lè mọ̀ lórí ilẹ̀ ayé pé oòrùn ti ṣíwọ́ iṣẹ́!”

      Gbé kókó yìí yẹ̀ wò ná: Tó o bá gbójú wòkè lọ́wọ́ alẹ́ wàá rí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìràwọ̀ lójú ọ̀run. Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ìràwọ̀ yìí ló ń mú agbára tó bùáyà jáde, bíi ti oòrùn. Ìwádìí táwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì ṣe sì jẹ́ ká mọ̀ pé ọ̀kẹ́ àìmọye ìràwọ̀ ló wà lójú ọ̀run!

      Ibo làwọn ìràwọ̀ yìí ti wá? Èyí tó pọ̀ jù lára àwọn tó ń ṣèwádìí gbà pé fún àwọn ìdí tí wọn kò tíì lóye síbẹ̀, ńṣe ni ayé àti ìsálú ọ̀run kan ṣàdédé wà, láti nǹkan bíi bílíọ̀nù mẹ́rìnlá ọdún sẹ́yìn. Àmọ́ ohun tí Bíbélì sọ nípa kókó yìí ṣe kedere, ó ní: “Ní ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀, Ọlọ́run dá ọ̀run àti ilẹ̀ ayé.” (Jẹ́nẹ́sísì. 1:1) Láìsí àní-àní, Ẹni tó dá àwọn ìràwọ̀ tí wọ́n jẹ́ nǹkan àrágbáyamúyamù yìí, la lè sọ ní tòótọ́ pé ó jẹ́ alágbára tó gadabú.— Aísáyà 40:26.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́