-
Ta Ni Yóò Yà Wá Kúrò Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2001 | October 15
-
-
14. Èé ṣe tí ìfẹ́ Ọlọ́run fi dá Pọ́ọ̀lù lójú, láìfi ìṣòro táwọn Kristẹni lè ní pè?
14 Ka Róòmù 8:38, 39. Kí ló mú un dá Pọ́ọ̀lù lójú pé kò sóhun tó lè ya àwọn Kristẹni kúrò nínú ìfẹ́ Ọlọ́run? Ó dájú pé ohun tí Pọ́ọ̀lù alára rí lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà wà lára ohun tó mú kó dá a lójú pé kò sí òkè ìṣòro tó lè mú kí ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní sí wa di tútù. (2 Kọ́ríńtì 11:23-27; Fílípì 4:13) Pẹ̀lúpẹ̀lù, Pọ́ọ̀lù mọ̀ nípa ète ayérayé Jèhófà àtohun tó ṣe fáwọn èèyàn Rẹ̀ ìgbàanì. Ǹjẹ́ ikú pàápàá lè borí ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní fáwọn tó fi ìṣòtítọ́ sìn ín? Rárá o! Ọlọ́run, ọba adánimágbàgbé, kò ní gbàgbé irú àwọn olóòótọ́ bẹ́ẹ̀ bí wọ́n bá kú, á sì jí wọn dìde nígbà tákòókò bá tó.—Lúùkù 20:37, 38; 1 Kọ́ríńtì 15:22-26.
-
-
Ta Ni Yóò Yà Wá Kúrò Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2001 | October 15
-
-
16 Gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni, kò sídìí láti bẹ̀rù pé èyíkéyìí nínú ohun tí Pọ́ọ̀lù pè ní “àwọn ohun tí ó wà níhìn-ín nísinsìnyí”—ìyẹn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àti ipò tó wà nínú ètò nǹkan ìsinsìnyí, tàbí “àwọn ohun tí ń bọ̀” lọ́jọ́ iwájú, lè ya Ọlọ́run nípa sáwọn èèyàn rẹ̀. Bí àwọn agbára ayé àtàwọn agbára òkùnkùn tilẹ̀ ń gbógun, ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í yẹ̀ yóò mẹ́sẹ̀ wa dúró. Bí Pọ́ọ̀lù ti tẹnu mọ́ ọn, kò sí “ibi gíga tàbí ibi jíjìn” tó lè dí ìfẹ́ Ọlọ́run lọ́wọ́. Bẹ́ẹ̀ ni o, kò sóhun tó ń múni rẹ̀wẹ̀sì tàbí tó ń jẹ gàba léni lórí, tó lè yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Ọlọ́run; bẹ́ẹ̀ náà ni kò sí ẹ̀dá èyíkéyìí tó lè ba àjọṣe tó wà láàárín Ẹlẹ́dàá àtàwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ olóòótọ́ jẹ́. Ìfẹ́ Ọlọ́run kì í kùnà; títí ayé ni.—1 Kọ́ríńtì 13:8.
-