-
Ṣe Ohun Táá Jẹ́ Kó O Borí Gbogbo Ìrònú Tí Kò Bá Ìmọ̀ Ọlọ́run Mu!Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019 | June
-
-
1. Ìkìlọ̀ wo ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fún àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró?
ÀPỌ́SÍTÉLÌ PỌ́Ọ̀LÙ kìlọ̀ fáwọn Kristẹni ẹni àmì òróró ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní pé: ‘Ẹ má ṣe jẹ́ kí ètò àwọn nǹkan yìí máa darí yín.’ (Róòmù 12:2) Kí nìdí tó fi fún wọn nírú ìkìlọ̀ bẹ́ẹ̀ bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará yẹn ti ya ara wọn sí mímọ́, tí Jèhófà sì ti fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ yàn wọ́n?—Róòmù 1:7.
2-3. Kí ni Sátánì ń ṣe kó lè kẹ̀yìn wa sí Jèhófà? Báwo la ṣe lè fa àwọn nǹkan tó ti “fìdí múlẹ̀ gbọn-in gbọn-in” tu lọ́kàn wa?
2 Pọ́ọ̀lù kíyè sí i pé àwọn Kristẹni kan ti fàyè gba èròkerò àti ọgbọ́n orí èèyàn tó kúnnú ayé Sátánì, ìdí nìyẹn tó fi kọ̀wé sí wọn. (Éfé. 4:17-19) Ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn Kristẹni yẹn lè ṣẹlẹ̀ sáwa náà. Sátánì tó jẹ́ ọlọ́run ètò àwọn nǹkan yìí ń wá bó ṣe máa mú ká kẹ̀yìn sí Jèhófà, onírúurú ọgbọ́n ló sì ń dá. Bí àpẹẹrẹ, tó bá kíyè sí pé a lẹ́mìí ìgbéraga tàbí pé a fẹ́ di gbajúmọ̀, ó lè lò ó láti dẹkùn mú wa. Ó sì tún lè lo àṣà ìbílẹ̀ wa, bá a ṣe kàwé tó àti ibi tá a gbé dàgbà láti mú ká máa ronú bíi tiẹ̀.
-
-
Ṣe Ohun Táá Jẹ́ Kó O Borí Gbogbo Ìrònú Tí Kò Bá Ìmọ̀ Ọlọ́run Mu!Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019 | June
-
-
Ẹ YÍ “ÈRÒ INÚ YÍN PA DÀ”
4. Ìyípadà wo ni ọ̀pọ̀ wa ṣe nígbà tá a kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́?
4 Ó ṣeé ṣe ká rántí àwọn ìyípadà tá a ṣe nígbà tá a kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́, tá a sì ya ara wa sí mímọ́ fún Jèhófà. Kíyẹn lè ṣeé ṣe, ọ̀pọ̀ lára wa ló jáwọ́ nínú àwọn ìwà tí kò tọ́. (1 Kọ́r. 6:9-11) A mà dúpẹ́ o pé Jèhófà ràn wá lọ́wọ́ láti borí àwọn ìwà burúkú yẹn!
5. Ìgbésẹ̀ méjì wo ni Róòmù 12:2 rọ̀ wá pé ká gbé?
5 Àmọ́ o, a ò gbọ́dọ̀ dẹra nù. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti jáwọ́ nínú àwọn ìwà burúkú tá à ń hù ká tó ṣèrìbọmi, síbẹ̀ ó yẹ ká túbọ̀ wà lójúfò ká sì yẹra fún ohunkóhun táá mú ká pa dà sẹ́yìn. Kí la lè ṣe tíyẹn ò fi ní ṣẹlẹ̀? Pọ́ọ̀lù sọ pé: ‘Ẹ má ṣe jẹ́ kí ètò àwọn nǹkan yìí máa darí yín, àmọ́ ẹ para dà nípa yíyí èrò inú yín pa dà.’ (Róòmù 12:2) Ẹsẹ yìí fi hàn pé ìgbésẹ̀ méjì kan wà tá a gbọ́dọ̀ gbé. Àkọ́kọ́, a gbọ́dọ̀ ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí ayé èṣù yìí “máa darí” wa. Èkejì, a gbọ́dọ̀ “para dà,” ní ti pé ká yí bá a ṣe ń ronú pa dà.
6. Kí la rí kọ́ nínú ọ̀rọ̀ Jésù tó wà nínú Mátíù 12:43-45?
6 Ìyípadà tí Pọ́ọ̀lù ń sọ kọjá ohun tó kàn hàn sójú táyé. Ó kan gbogbo apá ìgbésí ayé wa. (Wo àpótí náà, “Ṣé Lóòótọ́ Ni Mo Para Dà àbí Mò Ń Díbọ́n?”) A gbọ́dọ̀ yí èrò inú wa pa dà, ìyẹn ni pé ká ṣe ìyípadà nínú bá a ṣe ń ronú, bí nǹkan ṣe ń rí lára wa títí kan ohun tó ń sún wa ṣe nǹkan. Torí náà, ó yẹ kẹ́nì kọ̀ọ̀kan wa bi ara ẹ̀ pé, ‘Ṣé àwọn ìyípadà tí mò ń ṣe dénú mi àbí ojú ayé lásán ni mò ń ṣe?’ Ìbéèrè yìí ṣe pàtàkì gan-an, ó sì yẹ ká wá ìdáhùn sí i. Jésù sọ ohun tó yẹ ká ṣe nínú Mátíù 12:43-45. (Kà á.) Ọ̀rọ̀ Jésù tó wà nínú àwọn ẹsẹ yìí jẹ́ ká rí kókó pàtàkì kan, ìyẹn ni pé ká gbé èròkerò kúrò lọ́kàn nìkan ò tó, a tún gbọ́dọ̀ fi èrò tó bá ìfẹ́ Ọlọ́run mu kún ọkàn wa.
-