-
Báwo Ni Ìwọ Yóò Ṣe Dúró Níwájú Ìtẹ́ Ìdájọ́?Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | October 15
-
-
12 Nítorí náà, rírí tí Danieli rí Ọlọrun tí ó ‘jókòó lórí ìtẹ́’ túmọ̀ sí bíbọ̀ Rẹ̀ láti ṣèdájọ́. Dafidi ti kọrin ṣáájú pé: “Ìwọ [Jehofa] ni ó ti mú ìdájọ́ mi àti ìdí ọ̀ràn mi dúró; ìwọ ni ó jókòó lórí ìtẹ́, tí o ń ṣe ìdájọ́ òdodo.” (Orin Dafidi 9:4, 7) Joeli sì kọ̀wé pé: “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ni èmi [Jehofa] óò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.” (Joeli 3:12; fi wé Isaiah 16:5.) Jesu àti Paulu wà nínú ipò ìdájọ́, nínú èyí tí ẹ̀dá ènìyàn kan tí jókòó láti gbẹ́jọ́, tí ó sì ṣèdájọ́.b—Johannu 19:12-16; Ìṣe 23:3; 25:6.
-
-
Báwo Ni Ìwọ Yóò Ṣe Dúró Níwájú Ìtẹ́ Ìdájọ́?Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | October 15
-
-
b Ní ti kí àwọn Kristian máa pe ara wọn lẹ́jọ́ lẹ́nì kìíní-kejì, Paulu béèrè pé: “Ó ha jẹ́ awọn ọkùnrin tí a ń fojú-tẹ́ḿbẹ́lú ninu ìjọ ni ẹ̀yin ń fi sípò gẹ́gẹ́ bí awọn onídàájọ́ [ní òwuuru “ni ẹ̀yin ń bá jókòó bí”]?”—1 Korinti 6:4.
-