-
Bíborí Àìpé Ẹ̀dáIlé Ìṣọ́—2001 | March 15
-
-
4. Ọ̀rọ̀ ìṣítí tó wà nínú 1 Kọ́ríńtì 10:12, 13 wo ni Pọ́ọ̀lù sọ?
4 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù kọ̀wé sáwọn Kristẹni tí ń gbé ní Kọ́ríńtì—tó jẹ́ ìlú tí gbogbo èèyàn kà sí ìlú tó kún fún ìwàkiwà—ó fún wọn ní ìkìlọ̀ tó yẹ nípa ìdẹwò àti agbára ẹ̀ṣẹ̀. Ó sọ pé: “Kí ẹni tí ó bá rò pé òun dúró kíyè sára kí ó má bàa ṣubú. Kò sí ìdẹwò kankan tí ó ti bá yín bí kò ṣe ohun tí ó wọ́pọ̀ fún àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jẹ́ olùṣòtítọ́, kì yóò sì jẹ́ kí a dẹ yín wò ré kọjá ohun tí ẹ lè mú mọ́ra, ṣùgbọ́n pa pọ̀ pẹ̀lú ìdẹwò náà, òun yóò tún ṣe ọ̀nà àbájáde kí ẹ lè fara dà á.” (1 Kọ́ríńtì 10:12, 13) Gbogbo wa—lọ́mọdé lágbà, lọ́kùnrin àti lóbìnrin—là ń rí ọ̀pọ̀ ìdẹwò níléèwé, níbi iṣẹ́, tàbí níbòmíì. Torí náà, ẹ jẹ́ ká gbé ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù yẹ̀ wò, ká sì wo ẹ̀kọ́ táa lè rí kọ́ nínú rẹ̀.
-
-
Bíborí Àìpé Ẹ̀dáIlé Ìṣọ́—2001 | March 15
-
-
7. Èé ṣe tó fi ń tuni nínú láti mọ̀ pé àwọn èèyàn ti bá ìdẹwò jà, wọ́n sì ti borí?
7 Ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ, pé: “Kò sí ìdẹwò kankan tí ó ti bá yín bí kò ṣe ohun tí ó wọ́pọ̀ fún àwọn ènìyàn” mà tù wá nínú o! (1 Kọ́ríńtì 10:13) Àpọ́sítélì Pétérù kọ̀wé pé: “Ẹ mú ìdúró yín lòdì sí [Èṣù], ní dídúró gbọn-in nínú ìgbàgbọ́, ní mímọ̀ pé àwọn ohun kan náà ní ti ìyà jíjẹ ní ń ṣẹlẹ̀ sí gbogbo ẹgbẹ́ àwọn ará yín nínú ayé.” (1 Pétérù 5:9) Bẹ́ẹ̀ ni o, ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti bá irú ìdẹwò bẹ́ẹ̀ jà, tí wọ́n sì borí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run, àwa náà lè borí. Àmọ́ o, gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni tòótọ́ tí ń gbé nínú ayé oníwàkiwà yìí, gbogbo wa lè retí láti rí ìdẹwò, bó pẹ́ bó yá. Báwo wá ni a ṣe lè ní ìdánilójú pé a lè borí àìpé ẹ̀dá àti ìtẹ̀sí láti dẹ́ṣẹ̀?
-