ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọ̀nà Ìfẹ́ Kì í Kùnà Láé
    Ilé Ìṣọ́—1999 | February 15
    • 4. Ìjìnlẹ̀ òye wo ni Bíbélì fún wa nípa owú?

      4 Lẹ́yìn àwọn ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù kọ́kọ́ sọ nípa ìfẹ́, ó kọ̀wé sí àwọn ará Kọ́ríńtì pé: “Ìfẹ́ kì í jowú.” (1 Kọ́ríńtì 13:4) Owú lè fara hàn nígbà téèyàn bá bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara aásìkí tàbí àṣeyọrí àwọn ẹlòmíràn. Irú owú yìí ń jẹni run—nípa tara, ní ti èrò ìmọ̀lára, àti nípa tẹ̀mí.—Òwe 14:30; Róòmù 13:13; Jákọ́bù 3:14-16.

      5. Báwo ni ìfẹ́ ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti borí owú, tó bá jọ pé wọ́n gbé àǹfààní kan tó jẹ́ ti ìṣàkóso Ọlọ́run fò wá dá?

      5 Fún ìdí yìí, béèrè lọ́wọ́ ara rẹ pé, ‘Mo ha ń ṣe ìlara tó bá jọ pé wọ́n gbé àǹfààní tó jẹ́ ti ìṣàkóso Ọlọ́run fò mí dá?’ Bóo bá dáhùn bẹ́ẹ̀ ni, má bọkàn jẹ́ jù. Òǹkọ̀wé Bíbélì náà, Jákọ́bù, rán wa létí pé “ìtẹ̀sí láti ṣe ìlara” ń bẹ lára gbogbo ẹ̀dá ènìyàn aláìpé. (Jákọ́bù 4:5) Ìfẹ́ fún arákùnrin rẹ lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti mú ara rẹ padà bọ̀ sípò. Ó lè jẹ́ kó ṣeé ṣe fún ẹ láti máa bá àwọn aláyọ̀ yọ̀, kí o má sì kà á sí pé ṣe ni wọ́n kó iyán ẹ kéré tó bá jẹ́ pé ẹlòmíràn ló rí ìbùkún tàbí ọ̀rọ̀ ìyìn gbà.—Fi wé 1 Sámúẹ́lì 18:7-9.

      6. Ipò líle koko wo ló dìde nínú ìjọ Kọ́ríńtì ọ̀rúndún kìíní?

      6 Pọ́ọ̀lù fi kún un pé ìfẹ́ “kì í fọ́nnu, kì í wú fùkẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 13:4) Báa bá ní ẹ̀bùn kan tàbí táa mọ kiní kan-án ṣe, kò sídìí láti máa ganpá. Ó jọ pé èyí ni ìṣòro tó ń yọ àwọn kan tí ń jìjàdù ipò lẹ́nu, àwọn tó yọ́ wọnú ìjọ Kọ́ríńtì ìgbàanì. Ó lè jẹ́ pé ọ̀gá ni wọ́n nídìí ká ṣàlàyé ọ̀rọ̀ kó yéni, tàbí kó jẹ́ pé wọ́n mọ nǹkan-án ṣe lọ́nà tó gún régé. Ó lè jẹ́ pípè tí wọ́n ń pe àfiyèsí sára wọn ló dá kún pípín tí ìjọ náà pín sí oríṣiríṣi ẹgbẹ́. (1 Kọ́ríńtì 3:3, 4; 2 Kọ́ríńtì 12:20) Nígbà tí ọ̀ràn náà le dójú ẹ̀, Pọ́ọ̀lù wá ní láti bá àwọn ará Kọ́ríńtì wí kíkankíkan nítorí ‘fífaradà á fún àwọn aláìlọ́gbọ́n-nínú,’ tí Pọ́ọ̀lù bẹnu àtẹ́ lù, tó pè ní ‘àwọn àpọ́sítélì adárarégèé.’—2 Kọ́ríńtì 11:5, 19, 20.

      7, 8. Fi hàn láti inú Bíbélì báa ṣe lè lo ẹ̀bùn èyíkéyìí táa bá ní láti fi gbé ìṣọ̀kan lárugẹ.

      7 Irú ipò yẹn lè dìde lónìí. Fún àpẹẹrẹ, àwọn kan lè ní ìtẹ̀sí láti máa fi àwọn àṣeyọrí wọn nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ tàbí àwọn àǹfààní wọn nínú ètò àjọ Ọlọ́run yangàn. Ká tiẹ̀ sọ pé a ní òye tàbí ìmọ̀ kan tí àwọn mìíràn nínú ìjọ kò ní, ṣé ìyẹn wá ní ká máa wú fùkẹ̀? Bẹ́ẹ̀ rèé, ṣe ló yẹ ká máa fi ẹ̀bùn èyíkéyìí táa bá ní gbé ìṣọ̀kan lárugẹ—kì í ṣe ká máa fi gbéra ga.—Mátíù 23:12; 1 Pétérù 5:6.

      8 Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìjọ ní ọ̀pọ̀ ẹ̀yà ara, “Ọlọ́run pa ara pọ̀ ṣọ̀kan.” (1 Kọ́ríńtì 12:19-26) Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí a tú sí “pa pọ̀ ṣọ̀kan” tọ́ka sí àpòpọ̀ di ọ̀kan, bí ìgbà táa bá po onírúurú àwọ̀ pọ̀. Nítorí náà, kò yẹ kí ẹnikẹ́ni nínú ìjọ máa wú fùkẹ̀ nípa àwọn nǹkan tó mọ̀ ọ́n ṣe, kó sì wá fẹ́ máa jẹgàba lé àwọn yòókù lórí. Ìgbéraga àti dídu ipò kò yẹ ètò àjọ Ọlọ́run rárá.—Òwe 16:19; 1 Kọ́ríńtì 14:12; 1 Pétérù 5:2, 3.

  • Ọ̀nà Ìfẹ́ Kì í Kùnà Láé
    Ilé Ìṣọ́—1999 | February 15
    • 11. (a) Lọ́nà wo la lè gbà fi ìfẹ́ tó ní inú rere tó sì ń hùwà lọ́nà tó bójú mu hàn? (b) Báwo la ṣe lè fi hàn pé a kì í yọ̀ lórí àìṣòdodo?

      11 Pọ́ọ̀lù tún kọ̀wé pé ìfẹ́ ní “inú rere” àti pé “kì í hùwà lọ́nà tí kò bójú mu.” (1 Kọ́ríńtì 13:4, 5) Bẹ́ẹ̀ ni, ìfẹ́ kò ní jẹ́ ká hùwà lọ́nà tó fi hàn pé a jọ ara wa lójú, pé a ò mọ ohun tó tọ́, tàbí tó fi hàn pé a láfojúdi. Kàkà bẹ́ẹ̀, a óò máa gba tàwọn ẹlòmíràn rò. Fún àpẹẹrẹ, ẹni tó nífẹ̀ẹ́ yóò yàgò fún ṣíṣe àwọn nǹkan tí yóò yọ ẹ̀rí ọkàn àwọn ẹlòmíràn lẹ́nu. (Fi wé 1 Kọ́ríńtì 8:13.) Ìfẹ́ “kì í yọ̀ lórí àìṣòdodo, ṣùgbọ́n a máa yọ̀ pẹ̀lú òtítọ́.” (1 Kọ́ríńtì 13:6) Báa bá nífẹ̀ẹ́ òfin Jèhófà, a ò ní fojú kékeré wo ìṣekúṣe, tàbí kí nǹkan tí Ọlọ́run kórìíra jẹ́ ohun ìgbádùn fún wa. (Sáàmù 119:97) Ìfẹ́ yóò ràn wá lọ́wọ́ láti máa rí ayọ̀ nínú àwọn nǹkan tí ń gbéni ró, dípò àwọn nǹkan tí ń fa ìṣubú.—Róòmù 15:2; 1 Kọ́ríńtì 10:23, 24; 14:26.

  • Ọ̀nà Ìfẹ́ Kì í Kùnà Láé
    Ilé Ìṣọ́—1999 | February 15
    • 16. Nínú àwọn ipò wo ni ìfẹ́ ti lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní ìpamọ́ra?

      16 Pọ́ọ̀lù wá sọ fún wa pé “ìfẹ́ a máa ní ìpamọ́ra.” (1 Kọ́ríńtì 13:4) Ó ń jẹ́ kó ṣeé ṣe fún wa láti forí ti àwọn ipò ìṣòro, bóyá fún àkókò gígùn. Fún àpẹẹrẹ, ọ̀pọ̀ ọdún ni ọ̀pọ̀ Kristẹni ti ń gbé nínú ìdílé tí àwọn mẹ́ńbà rẹ̀ ti ń ṣe ẹ̀sìn ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Àwọn mìíràn jẹ́ àpọ́n, kì í ṣe nítorí pé wọ́n fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí pé wọn kò rí ẹni tí wọ́n lè fẹ́ “nínú Olúwa.” (1 Kọ́ríńtì 7:39; 2 Kọ́ríńtì 6:14) Àwọn kan tún wà tí àìsàn tí ń sọni di hẹ́gẹhẹ̀gẹ kò jẹ́ kí wọ́n gbádùn. (Gálátíà 4:13, 14; Fílípì 2:25-30) Ká sòótọ́, nínú ètò aláìpé yìí, kò sẹ́ni tí kò nílò ìfaradà lọ́nà kan tàbí òmíràn nínú ìgbésí ayé rẹ̀.—Mátíù 10:22; Jákọ́bù 1:12.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́