-
‘A Óò Gbé Àwọn Òkú Dìde’Ilé Ìṣọ́—1998 | July 1
-
-
7. (a) Ọ̀ràn pàtàkì wo ni Pọ́ọ̀lù darí àfiyèsí sí? (b) Àwọn wo ni ó rí Jésù lẹ́yìn tí a jí i dìde?
7 Nínú ẹsẹ méjì àkọ́kọ́ nínú 1 Kọ́ríńtì orí 15, Pọ́ọ̀lù gbé ẹṣin ọ̀rọ̀ tí ó fẹ́ jíròrò kalẹ̀, ó ní: “Ẹ̀yin ará, mo sọ ìhìn rere náà di mímọ̀ fún yín, èyí tí mo polongo fún yín, tí ẹ̀yin pẹ̀lú gbà, nínú èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú dúró, nípasẹ̀ èyí tí a tún ń gbà yín là, . . . àyàfi bí ó bá jẹ́ pé, ní ti tòótọ́, ẹ di onígbàgbọ́ lásán.” Bí àwọn ará Kọ́ríńtì bá kùnà láti dúró ṣinṣin nínú ìhìn rere, lásán ni wọ́n tẹ́wọ́ gba òtítọ́. Pọ́ọ̀lù ń bá a lọ pé: “Mo fi lé yín lọ́wọ́, lára àwọn ohun àkọ́kọ́, èyíinì tí èmi pẹ̀lú gbà, pé Kristi kú fún ẹ̀ṣẹ̀ wa gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí; àti pé a sin ín, bẹ́ẹ̀ ni, pé a ti gbé e dìde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí; àti pé ó fara han Kéfà, lẹ́yìn náà, àwọn méjìlá náà. Lẹ́yìn ìyẹn, ó fara han èyí tí ó ju ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àwọn ará lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, púpọ̀ jù lọ nínú àwọn tí wọ́n ṣì wà títí di ìsinsìnyí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn nínú ikú. Lẹ́yìn ìyẹn, ó fara han Jákọ́bù, lẹ́yìn náà, gbogbo àpọ́sítélì; ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn gbogbo rẹ̀, ó fara han èmi pẹ̀lú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a bí ní kògbókògbó.”—1 Kọ́ríńtì 15:3-8.
-
-
‘A Óò Gbé Àwọn Òkú Dìde’Ilé Ìṣọ́—1998 | July 1
-
-
9 Kristi tún fara han àwùjọ ńlá, “èyí tí ó ju ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àwọn ará.” Níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé Gálílì nìkan ni ó ti ní àwọn ọmọlẹ́yìn tó pọ̀ tó yẹn, èyí lè jẹ́ nígbà ìṣẹ̀lẹ̀ tí a ṣàlàyé nínú Mátíù 28:16-20, nígbà tí Jésù pàṣẹ sísọni di ọmọ ẹ̀yìn. Ẹ wo ẹ̀rí lílágbára tí àwọn wọ̀nyí yóò jẹ́! Àwọn kan ṣì wà láàyè ní ọdún 55 Sànmánì Tiwa, nígbà tí Pọ́ọ̀lù kọ lẹ́tà àkọ́kọ́ yìí sí àwọn ará Kọ́ríńtì. Ṣùgbọ́n o, ṣàkíyèsí pé àwọn tí ó ti kú ni a sọ pé wọ́n “ti sùn nínú ikú.” Nígbà yẹn, a kò tíì jí wọn dìde láti gba èrè wọn ti òkè ọ̀run.
-