-
Ṣé Òótọ́ Ni Pé Jésù Jíǹde?Ilé Ìṣọ́—2013 | March 1
-
-
Ó ṣẹlẹ̀ pé ọ̀rọ̀ nípa àjíǹde dà rú mọ́ àwọn Kristẹni kan ní ìlú Kọ́ríńtì lójú láyé àtijọ́. Àwọn míì kò sì gbà gbọ́ pé àjíǹde tiẹ̀ wà rárá. Nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù wá kọ ìwé kìíní sí àwọn Kristẹni tó wà níbẹ̀, ó sọ ohun tí ì bá yọrí sí ká ní kò sí àjíǹde lóòótọ́. Ó ní: “Ní tòótọ́, bí kò bá sí àjíǹde àwọn òkú, a jẹ́ pé a kò tíì gbé Kristi dìde. Ṣùgbọ́n bí a kò bá tíì gbé Kristi dìde, dájúdájú, asán ni ìwàásù wa, asán sì ni ìgbàgbọ́ wa. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, a rí wa pẹ̀lú ní ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run . . . Ìgbàgbọ́ yín jẹ́ aláìwúlò; ẹ ṣì wà nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín. Pẹ̀lúpẹ̀lù . . . àwọn tí ó sùn nínú ikú ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Kristi ṣègbé.”—1 Kọ́ríńtì 15:13-18.
“Ó fara han èyí tí ó ju ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àwọn ará lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo . . . Lẹ́yìn ìyẹn, ó fara han Jákọ́bù, lẹ́yìn náà, gbogbo àpọ́sítélì; ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn gbogbo rẹ̀, ó fara han èmi pẹ̀lú.”—1 Kọ́ríńtì 15:6-8
-
-
Ṣé Òótọ́ Ni Pé Jésù Jíǹde?Ilé Ìṣọ́—2013 | March 1
-
-
Ìyẹn nìkan kọ́ o. Pọ́ọ̀lù tún fi hàn pé ká ní Kristi kò jíǹde, asán àti òfo ni ìgbàgbọ́ àwọn Kristẹni ì bá já sí, orí irọ́ ni ìgbàgbọ́ wọn ì bá sì dá lé. Á wá já sí pé irọ́ ni Pọ́ọ̀lù àti àwọn tó kù ń pa pé Jésù jíǹde àti pé wọ́n parọ́ mọ́ Jèhófà Ọlọ́run pé ó jí i dìde. Yàtọ̀ síyẹn, a jẹ́ pé irọ́ gbuu tún ni bí wọ́n ṣe sọ pé Kristi “kú fún ẹ̀ṣẹ̀ wa.” Àbí, tí ẹni tí a mọ̀ sí Olùgbàlà fúnra rẹ̀ ò bá tíì bọ́ lọ́wọ́ ikú, báwo ló ṣe máa gba àwọn míì là? (1 Kọ́ríńtì 15:3) Ohun tí èyí máa túmọ̀ sí ni pé, ṣe ni àwọn Kristẹni tó kú, títí kan àwọn tó kú ikú ajẹ́rìíkú pàápàá, kàn fẹ̀mí ara wọn ṣòfò lásán, tí wọ́n rò pé àwọn máa jíǹde.
-