-
Àjíǹde Jésù Máa Jẹ́ Ká Ní Ìyè Àìnípẹ̀kun!Ilé Ìṣọ́—2013 | March 1
-
-
ÀJÍǸDE Jésù kì í ṣe ohun àrà ọ̀tọ̀ kan lásán tó ṣẹlẹ̀ nígbà àtijọ́ àmọ́ tí kò fi bẹ́ẹ̀ ṣe wá láǹfààní kankan lónìí. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ bó ti ṣe pàtàkì tó nígbà tó sọ pé: “A ti gbé Kristi dìde kúrò nínú òkú, àkọ́so nínú àwọn tí ó ti sùn nínú ikú. Nítorí níwọ̀n bí ikú ti wá nípasẹ̀ ènìyàn kan, àjíǹde òkú pẹ̀lú wá nípasẹ̀ ènìyàn kan. Nítorí gan-an gẹ́gẹ́ bí gbogbo ènìyàn ti ń kú nínú Ádámù, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni a ó sọ gbogbo ènìyàn di ààyè nínú Kristi.”—1 Kọ́ríńtì 15:20-22.
-
-
Àjíǹde Jésù Máa Jẹ́ Ká Ní Ìyè Àìnípẹ̀kun!Ilé Ìṣọ́—2013 | March 1
-
-
Ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ tẹ̀ lé e ṣàlàyé ohun tí àjíǹde Jésù mú kó ṣeé ṣe. Ó ní: “Níwọ̀n bí ikú ti wá nípasẹ̀ ènìyàn kan, àjíǹde òkú pẹ̀lú wá nípasẹ̀ ènìyàn kan.” Ẹ̀ṣẹ̀ àti àìpé tí a jogún láti ọ̀dọ̀ Ádámù ló sọ gbogbo wa di ẹni kíkú. Ṣùgbọ́n bí Jésù ṣe fi ẹ̀mí rẹ̀ tó jẹ́ pípé rà wá pa dà, ṣe ló mú kí àwọn tó bá kú lè ní àjíǹde kí wọ́n sì bọ́ lóko ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú. Lákòótán, Pọ́ọ̀lù wá sọ nínú Róòmù 6:23 pé: “Owó ọ̀yà tí ẹ̀ṣẹ̀ máa ń san ni ikú, ṣùgbọ́n ẹ̀bùn tí Ọlọ́run ń fi fúnni ni ìyè àìnípẹ̀kun nípasẹ̀ Kristi Jésù Olúwa wa.”
-