-
Ṣíṣàjọpín Ìtùnú Tí Jèhófà Ń PèsèIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
“Ọlọ́run Ìtùnú Gbogbo”
5. Ní àfikún sí ọ̀pọ̀ ìpọ́njú tí ó dé bá Pọ́ọ̀lù, kí ni ó tún nírìírí rẹ̀?
5 Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù jẹ́ ẹnì kan tí ó ní ìmọrírì jíjinlẹ̀ fún ìtùnú tí Ọlọ́run ń pèsè. Lẹ́yìn àkókò àdánwò ńlá ní Éṣíà àti ní Makedóníà, ara tù ú gidigidi nígbà tí ó gbọ́ pé ìjọ Kọ́ríńtì ti dáhùn padà lọ́nà rere sí lẹ́tà tí ó fi bá wọn wí. Èyí sún un láti kọ lẹ́tà kejì sí wọn, tí ó ní àwọn ọ̀rọ̀ ìyìn tí ó tẹ̀ lé e yìí pé: “Ìbùkún ni fún Ọlọ́run àti Bàbá Olúwa wa Jésù Kristi, Bàbá àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo, ẹni tí ń tù wá nínú nínú gbogbo ìpọ́njú wa.”—Kọ́ríńtì Kejì 1:3, 4.
6. Kí ni a rí kọ́ láti inú àwọn ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù tí a rí nínú Kọ́ríńtì Kejì 1:3, 4?
6 Ọ̀rọ́ pọ̀ nínú àwọn ọ̀rọ̀ onímìísí wọ̀nyí. Ẹ jẹ́ kí a fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù bá sọ̀rọ̀ ìyìn tàbí dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, tàbí tí ó bá tọrọ nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀ nínú lẹ́tà rẹ̀, a sábà máa ń rí i pé ó máa ń fi ìmọrírì jíjinlẹ̀ hàn fún Jésù, Orí ìjọ Kristẹni. (Róòmù 1:8; 7:25; Éfésù 1:3; Hébérù 13:20, 21) Nítorí náà, Pọ́ọ̀lù lo gbólóhùn ọ̀rọ̀ ìyìn yìí fún “Ọlọ́run àti Bàbá Olúwa wa Jésù Kristi.” Lẹ́yìn náà, fún ìgbà àkọ́kọ́ nínú àwọn ìwé rẹ̀, ó lo ọ̀rọ̀ orúkọ èdè Gíríìkì kan tí a túmọ̀ sí “àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́.” Ọ̀rọ̀ orúkọ yìí wá láti inú ọ̀rọ̀ kan tí a ń lò láti fi ìbànújẹ́ hàn nígbà tí ẹlòmíràn bá ń jìyà. Nípa báyìí, Pọ́ọ̀lù ń ṣàpèjúwe ìmọ̀lára oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ ti Ọlọ́run fún èyíkéyìí lára àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ olùṣòtítọ́ tí ń jìyà ìpọ́njú—ìmọ̀lára oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ tí ó ń sún Ọlọ́run láti gbégbèésẹ̀ tàánútàánú nítorí wọn. Ní paríparí rẹ̀, Pọ́ọ̀lù wo Jèhófà gẹ́gẹ́ bí orísun ànímọ́ fífani mọ́ra yìí nípa pípè é ní “Bàbá àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́.”
7. Èé ṣe tí a fi lè sọ pé Jèhófà ni “Ọlọ́run ìtùnú gbogbo”?
7 “Àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́” ti Ọlọ́run ń mú ìtura wá fún ẹni tí ìpọ́njú dé bá. Nítorí náà, Pọ́ọ̀lù tẹ̀ síwájú láti ṣàpèjúwe Jèhófà gẹ́gẹ́ bí “Ọlọ́run ìtùnú gbogbo.” Nípa báyìí, ìtùnú yòó wù tí a lè rí gbà láti ara inú rere ti àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ ẹni, a lè wo Jèhófà gẹ́gẹ́ bí orísun rẹ̀. Kò sí ìtùnú gidi, tí ó wà pẹ́ títí, tí kò pilẹ̀ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run. Síwájú sí i, òun ni ó dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀, tí ó tipa báyìí mú kí ó ṣeé ṣe fún wa láti jẹ́ olùtùnú. Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run sì ni ó ń sún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láti fi àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ hàn sí àwọn tí ó nílò ìtùnú.
-
-
Ṣíṣàjọpín Ìtùnú Tí Jèhófà Ń PèsèIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
8. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ọlọ́run kọ́ ni orísun àwọn àdánwò wa, ipa ṣíṣàǹfààní wo ni ìfaradà wa lè ní lórí wa?
8 Bí Jèhófà Ọlọ́run tilẹ̀ fàyè gba onírúurú àdánwò tí ń ṣẹlẹ̀ sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ olùṣòtítọ́, òun kò fìgbà kan rí jẹ́ orísun irú àwọn àdánwò bẹ́ẹ̀. (Jákọ́bù 1:13) Ṣùgbọ́n, ìtùnú tí òun ń pèsè nígbà tí a bá ń fara da ìpọ́njú lè kọ́ wa láti túbọ̀ wà lójúfò sí àìní àwọn ẹlòmíràn. Kí ni àbájáde rẹ̀? “Kí àwa lè tu àwọn wọnnì tí wọ́n wà nínú ìpọ́njú èyíkéyìí nínú nípasẹ̀ ìtùnú tí Ọlọ́run fi ń tu àwa tìkára wa nínú.” (Kọ́ríńtì Kejì 1:4) Nípa báyìí, Jèhófà ń kọ́ wa láti jẹ́ ẹní tí ń ṣàjọpín ìtùnú rẹ̀ lọ́nà gbígbéṣẹ́ pẹ̀lú àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wa àti pẹ̀lú àwọn tí a ń bá pàdé nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa bí a ti ń fara wé Kristi, tí a sì “ń tu gbogbo àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.”—Aísáyà 61:2; Mátíù 5:4.
-