-
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Tá A Fi Ń Ṣe Ìrànwọ́Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
-
-
6. (a) Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi sọ pé iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ nígbà àjálù jẹ́ apá kan ìjọsìn wa? (b) Ṣàlàyé bí a ṣe ń ṣe iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ nígbà àjálù kárí ayé lónìí. (Wo àpótí náà, “Nígbà Tí Àjálù Bá Ṣẹlẹ̀!” lójú ìwé 214.)
6 Pọ́ọ̀lù jẹ́ kó yé àwọn ará tó wà ní Kọ́ríńtì pé iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ fáwọn Kristẹni ẹlẹgbẹ́ wọn nígbà ìṣòro jẹ́ ara iṣẹ́ òjíṣẹ́ àti ìjọsìn wọn sí Jèhófà. Pọ́ọ̀lù gbà pé Kristẹni tó bá ń ṣèrànwọ́ fún onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ń fi hàn pé òun ní “ẹ̀mí ìtẹríba fún ìhìn rere nípa Kristi.” (2 Kọ́r. 9:13) Nítorí náà, Kristẹni tó bá ń fi ẹ̀kọ́ Kristi sílò kò ní ṣàì ṣèrànwọ́ fún àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Pọ́ọ̀lù tún sọ pé ohun tí àwọn ará ń ṣe yìí jẹ́ “inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run títayọ ré kọjá.” (2 Kọ́r. 9:14; 1 Pét. 4:10) Tó bá di ọ̀rọ̀ ṣíṣe ìrànwọ́ fáwọn ará wa tó wà nínú ìṣòro, tó fi mọ́ iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ nígbà àjálù, Ile-Iṣọ Na June 1, 1976 sọ pé: “Àwa kò gbọ́dọ̀ ṣiyè méjì pé Jèhófà àti Jésù ka irú iṣẹ́ báyìí sí nǹkan pàtàkì.” Ó dá wa lójú ní tòótọ́ pé irú iṣẹ́ ìsìn mímọ́ kan tó ṣeyebíye ni iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ nígbà àjálù jẹ́.—Róòmù 12:1, 7; 2 Kọ́r. 8:7; Héb. 13:16.
-
-
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Tá A Fi Ń Ṣe Ìrànwọ́Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
-
-
7, 8. Kí nìdí àkọ́kọ́ tá a fi ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí a fi ń ṣe ìrànwọ́ nígbà ìṣòro? Ṣàlàyé.
7 Kí nìdí tá a fi ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ tá a fi ń ṣe ìrànwọ́ fáwọn tí àjálù bá? Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù dáhùn ìbéèrè yìí nínú ìwé kejì tó kọ sí àwọn ará ní Kọ́ríńtì. (Ka 2 Kọ́ríńtì 9:11-15.) Nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì yẹn, Pọ́ọ̀lù sọ ìdí pàtàkì mẹ́ta tá a fi ń ṣe “iṣẹ́ òjíṣẹ́ iṣẹ́ ìsìn fún gbogbo ènìyàn yìí,” ìyẹn, iṣẹ́ ìrànwọ́ nígbà àjálù. Ní báyìí, a fẹ́ gbé ìdí mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yẹ̀ wò lọ́kọ̀ọ̀kan.
8 Àkọ́kọ́, iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí a fi ń ṣe ìrànwọ́ nígbà ìṣòro ń yin Jèhófà lógo. Ẹ kíyè sí pé nínú ẹsẹ Bíbélì márààrún tá a kà yẹn, ọ̀dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run ni Pọ́ọ̀lù darí àfiyèsí àwọn ará sí. Ó rán wọn létí nípa ‘ìfọpẹ́hàn fún Ọlọ́run’ àti “ọ̀pọ̀ ìfọpẹ́hàn fún Ọlọ́run.” (Ẹsẹ 11 àti 12) Ó tún sọ bí iṣẹ́ ṣíṣe ìrànwọ́ nígbà àjálù yìí ṣe máa ń sún àwọn Kristẹni láti “yin Ọlọ́run lógo” kí wọ́n sì tún yìn ín nítorí “inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí” rẹ̀ “títayọ ré kọjá.” (Ẹsẹ 13 àti 14) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ lórí iṣẹ́ òjíṣẹ́ fún àwọn ẹni mímọ́ náà, ìyẹn iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí a fi ń ṣe ìrànwọ́ fáwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wa nígbà ìṣòro, ó sọ pé: “Ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run.”—Ẹsẹ 15; 1 Pét. 4:11.
-