-
Ṣíṣàjọpín Ìtùnú Tí Jèhófà Ń PèsèIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
Ìpọ́njú Pọ́ọ̀lù ní Éṣíà
13, 14. (a) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe ṣàpèjúwe àkókò ìpọ́njú líle koko tí ó nírìírí rẹ̀ ní Éṣíà? (b) Ìṣẹ̀lẹ̀ wo ni Pọ́ọ̀lù ti lè ní lọ́kàn?
13 A kò lè fi irú ìyà tí ìjọ Kọ́ríńtì jẹ títí di àkókò yìí wé ọ̀pọ̀ ìpọ́njú tí Pọ́ọ̀lù ní láti fara dà. Nípa báyìí, ó lè rán wọn létí pé: “Àwa kò fẹ́ kí ẹ ṣe aláìmọ̀, ẹ̀yin ará, nípa ìpọ́njú tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa ní àgbègbè Éṣíà, pé àwa wà lábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ dé góńgó ré kọjá okun wa, tó bẹ́ẹ̀ tí a kò ní ìdánilójú rárá nípa ìwàláàyè wa pàápàá. Ní ti tòótọ́, a nímọ̀lára nínú ara wa pé a ti gba ìdájọ́ ìkú. Èyí jẹ́ kí a má baà ní ìgbẹ́kẹ̀lé wa nínú ara wa, bí kò ṣe nínú Ọlọ́run ẹni tí ń gbé òkú dìde. Láti inú irúfẹ́ ohun ńlá kan bẹ́ẹ̀ bí ikú ni òun ti gbà wá sílẹ̀ tí òun yóò sì gbà wá sílẹ̀; ìrètí wa sì wà nínú rẹ̀ pé òun yóò gbà wá sílẹ̀ síwájú sí i pẹ̀lú.”—Kọ́ríńtì Kejì 1:8-10.
14 Àwọn akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ Bíbélì mélòó kan gbà gbọ́ pé Pọ́ọ̀lù ń tọ́ka sí rúkèrúdò tí ó ṣẹlẹ̀ ní Éfésù, tí ì bá ti gba ìwàláàyè Pọ́ọ̀lù àti ti àwọn ará Makedóníà méjì tí ń bá a rìnrìn àjò, Gáyọ́sì àti Àrísítákọ́sì. A fipá mú àwọn Kristẹni méjì yìí lọ sí gbọ̀ngàn ìwòran tí àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn kún fọ́fọ́, tí wọ́n ń “kígbe fún nǹkan bíi wákàtí méjì pé: ‘Títóbi ni Átẹ́mísì [abo ọlọ́run] ti àwọn ará Éfésù!’” Àsẹ̀yìnwá àsẹ̀yìnbọ̀, ìjòyè ìlú kan kẹ́sẹ járí ní pípa àwùjọ náà lẹ́nu mọ́. Ewu tí ó wu ìwàláàyè Gáyọ́sì àti Àrísítákọ́sì yìí gbọ́dọ̀ ti dààmú Pọ́ọ̀lù gidigidi. Ní tòótọ́, ó fẹ́ wọlé lọ, kí ó sì bá àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn agbawèrèmẹ́sìn náà sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n a dá a dúró láti má ṣe fi ìwàláàyè rẹ̀ wewu lọ́nà yìí.—Ìṣe 19:26-41.
15. Ipò tí ó légbá kan wo ni ó lè jẹ́ pé a ṣàpèjúwe nínú Kọ́ríńtì Kìíní 15:32?
15 Ṣùgbọ́n, ó lè jẹ́ pé ohun tí Pọ́ọ̀lù ń ṣàpèjúwe ré kọjá ìṣẹ̀lẹ̀ tí a mẹ́nu kàn tán yìí fíìfíì. Nínú lẹ́tà rẹ̀ àkọ́kọ́ sí àwọn ará Kọ́ríńtì, Pọ́ọ̀lù béèrè pé: “Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn, bí mo bá ti bá àwọn ẹranko ẹhànnà jà ní Éfésù, ire kí ni ó jẹ́ fún mi?” (Kọ́ríńtì Kìíní 15:32) Èyí lè túmọ̀ sí pé kì í ṣe àwọn ènìyàn oníwà ẹranko nìkan ni ó wu ìwàláàyè Pọ́ọ̀lù léwu, ṣùgbọ́n àwọn ẹranko ẹhànnà ní ti gidi nínú pápá ìṣeré Éfésù wu ú léwu pẹ̀lú. Nígbà míràn, a máa ń jẹ àwọn ọ̀daràn níyà nípa fífipá mú wọn láti bá àwọn ẹranko ẹhànnà jà, nígbà tí àwọn àwùjọ tí òùngbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ yóò sì máa wòran. Bí Pọ́ọ̀lù bá ní in lọ́kàn pé òun kojú àwọn ẹranko ẹhànnà ní ti gidi, ó ti ní láti jẹ́ pé nígbà tí ọ̀ràn náà dójú ọ̀gbagadè, ọ̀nà ìyanu ni a fi gbà á sílẹ̀, kúrò lọ́wọ́ ikú òǹrorò, gan-an gẹ́gẹ́ bí a ti dáàbò bo Dáníẹ́lì kúrò lẹ́nu àwọn kìnnìún ní ti gidi.—Dáníẹ́lì 6:22.
-
-
Ṣíṣàjọpín Ìtùnú Tí Jèhófà Ń PèsèIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
16. (a) Èé ṣe tí ọ̀pọ̀ Ẹlẹ́rìí Jèhófà lónìí fi lè lóye àwọn ìpọ́njú tí ó dé bá Pọ́ọ̀lù? (b) Kí ni ó lè dá wa lójú nípa àwọn tí wọ́n kú nítorí ìgbàgbọ́ wọn? (c) Kí ni ipa rere tí yíyè bọ́ tí àwọn Kristẹni yè bọ́ lọ́wọ́ ikú ti ní?
16 Ọ̀pọ̀ Kristẹni lónìí lè lóye irú àwọn ìpọ́njú tí ó dé bá Pọ́ọ̀lù. (Kọ́ríńtì Kejì 11:23-27) Lónìí, pẹ̀lú, àwọn Kristẹni ti wà “lábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ dé góńgó ré kọjá okun [wọn],” ọ̀pọ̀ sì ti kojú àwọn ipò nínú èyí tí wọn ‘kò ní ìdánilójú rárá nípa ìwàláàyè wọn.’ (Kọ́ríńtì Kejì 1:8) Àwọn òṣìkàpànìyàn àti àwọn òǹrorò onínúnibíni ti pa àwọn kan. A lè ní ìdánilójú pé agbára Ọlọ́run tí ń tuni nínú mú kí wọn lè fara dà àti pé wọ́n kú pẹ̀lú ọkàn-àyà àti èrò inú tí ó dúró gbọn-in-gbọn-in lórí ìmúṣẹ ìrètí wọn, yálà ìrètí ti ọ̀run tàbí ti orí ilẹ̀ ayé. (Kọ́ríńtì Kìíní 10:13; Fílípì 4:13; Ìṣípayá 2:10) Nínú àwọn ọ̀ràn míràn, Jèhófà ti fọgbọ́n darí àwọn nǹkan, a sì ti gba àwọn ará wa sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú. Dájúdájú, àwọn ti wọ́n ti rí ìgbàlà lọ́nà bẹ́ẹ̀ ti mú ìgbẹ́kẹ̀lé tí ó pọ̀ sí i dàgbà “nínú Ọlọ́run ẹni tí ń gbé òkú dìde.” (Kọ́ríńtì Kejì 1:9) Lẹ́yìn náà, wọ́n lè sọ̀rọ̀ àní pẹ̀lú ìdánilójú gidigidi bí wọ́n ti ń ṣàjọpín ìhìn iṣẹ́ Ọlọ́run tí ń tuni nínú pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn.—Mátíù 24:14.
-