-
Máa “Ṣe Ìdájọ́ Òdodo” Bó O Ṣe Ń Bá Ọlọ́run RìnSún Mọ́ Jèhófà
-
-
4. Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà ń retí pé ká máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà òdodo òun?
4 Jèhófà ń retí pé ká máa tẹ̀ lé ìlànà òun nípa ohun tó tọ́ àti ohun tí kò tọ́. A mọ̀ pé àwọn ìlànà Jèhófà jẹ́ òdodo, wọ́n sì bá ìdájọ́ òdodo mu, torí náà tá a bá ń tẹ̀ lé àwọn ìlànà rẹ̀ èyí á fi hàn pé àwa náà nífẹ̀ẹ́ òdodo àti ìdájọ́ òdodo. Àìsáyà 1:17 sọ pé: “Ẹ kọ́ bí ẹ ṣe máa ṣe rere, ẹ wá ìdájọ́ òdodo.” Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tún sọ pé ká “wá òdodo.” (Sefanáyà 2:3) Bákan náà, ó rọ̀ wá pé ká “gbé ìwà tuntun wọ̀, èyí tí a dá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run nínú òdodo tòótọ.” (Éfésù 4:24) Tá a bá ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti tẹ̀ lé àwọn ìlànà Jèhófà, àá máa yẹra fún ìwà ipá, ìwà àìmọ́ àti ìṣekúṣe, torí pé irú àwọn ìwà yìí lòdì sí ìlànà Jèhófà.—Sáàmù 11:5; Éfésù 5:3-5.
-
-
Máa “Ṣe Ìdájọ́ Òdodo” Bó O Ṣe Ń Bá Ọlọ́run RìnSún Mọ́ Jèhófà
-
-
6 Torí pé a jẹ́ aláìpé, kì í ṣe gbogbo ìgbà ló máa ń rọrùn fún wa láti ṣe ohun tó tọ́. Ìdí nìyẹn tá a fi gbọ́dọ̀ bọ́ ìwà àtijọ́ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn àṣà rẹ̀, ká sì gbé tuntun wọ̀. Nígbà tí Bíbélì ń sọ̀rọ̀ nípa ìwà tuntun yìí, ó ní ‘à ń sọ ọ́ di tuntun’ nípasẹ̀ ìmọ̀ tó péye. (Kólósè 3:9, 10) Gbólóhùn náà, ‘à ń sọ ọ́ di tuntun,’ jẹ́ ká mọ̀ pé tá a bá fẹ́ gbé ìwà tuntun wọ̀, kì í ṣe nǹkan tá a máa ṣe lẹ́ẹ̀kan tá a sì máa dáwọ́ dúró. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe làá máa ṣe é nìṣó, èyí sì gba ìsapá. Àmọ́ bó ti wù ká sapá tó, a ṣì lè ṣàṣìṣe nínú èrò, ọ̀rọ̀ tàbí ìṣe wa torí pé aláìpé ni wá.—Róòmù 7:14-20; Jémíìsì 3:2.
-