-
‘Ẹ Máa Bá a Lọ Ní Dídáríji Ara Yín Lẹ́nì Kíní Kejì’Ilé Ìṣọ́—1997 | December 1
-
-
5. Ìdí pàtàkì wo fún dídáríji àwọn ẹlòmíràn ni a fi hàn nínú Éfésù 5:1?
5 Ìdí pàtàkì kan tí ó wà fún dídáríji àwọn ẹlòmíràn ni a fi hàn nínú Éfésù 5:1: “Nítorí náà, ẹ di aláfarawé Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí í ṣe olùfẹ́ ọ̀wọ́n.” Lọ́nà wo ni ó fi yẹ kí a “di aláfarawé Ọlọ́run”? Ọ̀rọ̀ náà, “nítorí náà,” so gbólóhùn náà mọ́ ẹsẹ ìṣáájú, tí ó sọ pé: “Ẹ di onínú rere sí ara yín lẹ́nì kíní kejì, ní fífi ìyọ́nú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ hàn, kí ẹ máa dárí ji ara yín lẹ́nì kíní kejì fàlàlà gan-an gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run pẹ̀lú ti tipasẹ̀ Kristi dárí jì yín fàlàlà.” (Éfésù 4:32) Bẹ́ẹ̀ ni, nígbà tí ó bá di ọ̀ràn ìdáríjì, ó yẹ kí a jẹ́ aláfarawé Ọlọ́run. Bí ọmọdékùnrin kan ṣe ń fẹ́ láti dà bíi bàbá rẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ó ṣe yẹ kí àwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí Jèhófà nífẹ̀ẹ́ gidigidi, fẹ́ láti dà bíi Bàbá wa ọ̀run tí ń dárí jì. Ẹ wo bí inú Jèhófà yóò ti dùn tó bí ó bá bojú wolẹ̀ láti ọ̀run tí ó sì rí àwọn ọmọ rẹ̀ orí ilẹ̀ ayé tí wọ́n ń gbìyànjú láti dà bíi rẹ̀ nípa dídáríji ara wá lẹ́nì kíní kejì!—Lúùkù 6:35, 36; fi wé Mátíù 5:44-48.
6. Lọ́nà wo ni ìyàtọ̀ gígadabú fi wà láàárín ìdáríjì Jèhófà àti tiwa?
6 Lóòótọ́, a kò lè dárí jini lọ́nà pípé pérépéré bíi ti Jèhófà láéláé. Ṣùgbọ́n ìdí gan-an nìyẹn tí ó fi yẹ kí a máa dárí ji ara wa. Rò ó wò ná: Ìyàtọ̀ gígadabú wà láàárín ìdáríjì Jèhófà àti tiwa. (Aísáyà 55:7-9) Nígbà tí a bá dárí ji àwọn tí ó ṣẹ̀ wá, ó sábà máa ń jẹ́ pẹ̀lú èrò náà pé bó pẹ́ bó yá, a óò fẹ́ kí wọ́n ṣojú rere kan náà sí wa nípa dídáríjì wá. Ní ti ẹ̀dá ènìyàn, ó sábà máa ń jẹ́ ọ̀ràn ẹlẹ́ṣẹ̀ tí ń dárí ji ẹlẹ́ṣẹ̀. Ṣùgbọ́n, ní ti Jèhófà, ọ̀nà kan ni ìdáríjì náà. Ó ń dárí jì wá, ṣùgbọ́n kò lè sí ìdí kankan fún wa láti dárí jì í. Bí Jèhófà, tí kì í dẹ́ṣẹ̀, bá lè fi ìfẹ́ dárí jì wá pátápátá porogodo, kò ha yẹ kí àwa ẹ̀dá ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ gbìyànjú láti dárí ji ara wa bí?—Mátíù 6:12.
-
-
‘Ẹ Máa Bá a Lọ Ní Dídáríji Ara Yín Lẹ́nì Kíní Kejì’Ilé Ìṣọ́—1997 | December 1
-
-
11. Nígbà tí àwọn ẹlòmíràn bá ṣẹ̀ wá, kí ní lè ràn wá lọ́wọ́ láti dárí jì wọ́n?
11 Ṣùgbọ́n, bí àwọn ẹlòmíràn bá ṣẹ̀ wá ńkọ́, ní dídá ọgbẹ́ tí ó ṣeé tètè rí sí wa lára? Bí ẹ̀ṣẹ̀ náà kò bá burú jù, a lè máà ní ìṣòro púpọ̀ ní lílo ìmọ̀ràn Bíbélì náà láti “dárí ji ara yín lẹ́nì kíní kejì fàlàlà.” (Éfésù 4:32) Irú ìmúratán bẹ́ẹ̀ láti dárí jini wà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Pétérù náà tí a mí sí pé: “Lékè ohun gbogbo, ẹ ní ìfẹ́ gbígbóná janjan fún ara yín lẹ́nì kíní kejì, nítorí ìfẹ́ a máa bo ògìdìgbó ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.” (Pétérù Kíní 4:8) Níní i lọ́kàn pé àwa pẹ̀lú jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ ń ràn wá lọ́wọ́ láti yọ̀ǹda fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ẹlòmíràn. Nígbà tí a bá sì tipa báyìí dárí jini, a óò tú kùnrùngbùn náà jáde dípò tí a óò fi dì í sínú. Ìyọrísí rẹ̀ ni pé, ipò ìbátan wa pẹ̀lú oníláìfí náà lè má bà jẹ́ títí lọ, a sì tún lè ṣèrànwọ́ láti pa àlàáfíà ìjọ tí ó ṣeyebíye mọ́. (Róòmù 14:19) Bí ọjọ́ ti ń gorí ọjọ́, a lè máà rántí ohun tí ó ṣe mọ́ rárá.
-