-
Bá A Ṣe Lè Ṣe Ìpinnu Tó DáaGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
3. Jẹ́ kí Bíbélì máa tọ́ ẹ sọ́nà
Báwo ni àwọn ìlànà Bíbélì ṣe lè tọ́ wa sọ́nà tá a bá fẹ́ ṣe ìpinnu? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Òmìnira wo ni Jèhófà fún gbogbo wa?
Kí nìdí tí Jèhófà fi fún wa lómìnira láti yan ohun tó wù wá?
Àwọn nǹkan wo ni Jèhófà fún wa tó máa jẹ́ ká lo òmìnira wa lọ́nà tó dáa jù lọ?
Kó o lè rí àpẹẹrẹ ìlànà Bíbélì kan, ka Éfésù 5:15, 16. Lẹ́yìn náà, sọ bó o ṣe lè ‘lo àkókò ẹ lọ́nà tó dára jù lọ’ kó o lè . . .
máa ka Bíbélì lójoojúmọ́.
jẹ́ ọkọ, aya, òbí tàbí ọmọ rere.
máa lọ sáwọn ìpàdé ìjọ.
-
-
Yan Eré Ìnàjú Táá Múnú Jèhófà DùnGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
2. Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa lo àkókò tó pọ̀ jù nídìí eré ìnàjú?
Tí eré ìnàjú tá a fẹ́ràn bá tiẹ̀ bójú mu, a gbọ́dọ̀ kíyè sára kó má di pé àá máa lo àkókò tó pọ̀ jù nídìí ẹ̀. Torí tá ò bá ṣọ́ra, a lè má ráyè fáwọn nǹkan tó ṣe pàtàkì jù. Bíbélì sọ pé ká máa “lo àkókò [wa] lọ́nà tó dára jù lọ.”—Ka Éfésù 5:15, 16.
-
-
Yan Eré Ìnàjú Táá Múnú Jèhófà DùnGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
4. Máa fọgbọ́n lo àkókò rẹ
Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn nǹkan tí kò tọ́ kọ́ ni arákùnrin tá a rí nínú fídíò yẹn ń wò, kí ló fi hàn pé kò fọgbọ́n lo àkókò rẹ̀?
Ka Fílípì 1:10, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Báwo ni ẹsẹ Bíbélì yìí ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti máa fọgbọ́n lo àkókò wa tá a bá fẹ́ ṣe eré ìnàjú?
-