ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Báa Ṣe Lè Mọ Àìlera Tẹ̀mí Kí A sì Borí Rẹ̀
    Ilé Ìṣọ́—1999 | April 15
    • Níwọ̀n ìgbà tó jẹ́ pé ogun tẹ̀mí là ń jà—ogun kan tó wé mọ́ ṣíṣàkóso èrò inú àti ọkàn-àyà Kristẹni—a gbọ́dọ̀ sa gbogbo ipá wa láti dáàbò bo agbára ìrònú wa. Rántí pé àwọn nǹkan wọ̀nyí jẹ́ apá kan ìhámọ́ra tẹ̀mí wa, “ìgbàyà òdodo,” tí ń dáàbò bo ọkàn-àyà wa, àti “àṣíborí ìgbàlà,” tí ń dáàbò bo èrò inú wa. Kíkọ́ bí a óò ṣe lo àwọn ìpèsè wọ̀nyí dáadáa lè túmọ̀ sí pé a ó jagun àjàyè tàbí ká bógun lọ.—Éfésù 6:14-17; Òwe 4:23; Róòmù 12:2.

  • Báa Ṣe Lè Mọ Àìlera Tẹ̀mí Kí A sì Borí Rẹ̀
    Ilé Ìṣọ́—1999 | April 15
    • Fífi “àṣíborí ìgbàlà” dé orí wa wé mọ́ fífi àwọn ìbùkún àgbàyanu tí ń bẹ níwájú sọ́kàn dáradára, ká má ṣe jẹ́ kí àwọn ohun yòdòyindin, àwọn ohun yòyòyò ayé fà wá kúrò lójú ọ̀nà. (Hébérù 12:2, 3; 1 Jòhánù 2:16) Níní ojú ìwòye yìí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti fi ire tẹ̀mí ṣáájú èrè nípa ti ara tàbí èyí tó jẹ́ fún àǹfààní ara wa. (Mátíù 6:33) Nípa báyìí, láti lè mọ̀ dájú pé àṣíborí yìí bò wá lórí dáadáa, a gbọ́dọ̀ bi ara wa léèrè láìṣàbòsí, pé: Kí ni mò ń lépa nínú ìgbésí ayé mi? Ǹjẹ́ mo tilẹ̀ ní àwọn góńgó tẹ̀mí pàtó? Kí ni mò ń ṣe kí ọwọ́ mi lè tẹ̀ wọ́n? Yálà ọ̀kan lára àṣẹ́kù ẹni àmì òróró Kristẹni ni wá ni o tàbí a wà lára ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ ti “ogunlọ́gọ̀ ńlá,” ó yẹ ká fara wé Pọ́ọ̀lù, ẹni tó sọ pé: “Èmi kò tíì ka ara mi sí ẹni tí ó ti gbá a mú nísinsìnyí; ṣùgbọ́n ohun kan wà nípa rẹ̀: Ní gbígbàgbé àwọn ohun tí ń bẹ lẹ́yìn àti nínàgà sí àwọn ohun tí ń bẹ níwájú, mo ń lépa góńgó náà nìṣó.”—Ìṣípayá 7:9; Fílípì 3:13, 14.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́