-
Ohun Tó O Lè Ṣe Láti Máa Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì NìṣóGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
4. Fi ọwọ́ pàtàkì mú ẹ̀kọ́ Bíbélì tó ò ń kọ́
Nígbà míì ọwọ́ wa máa ń dí gan-an, táá sì máa ṣe wá bíi pé a ò lè ráyè láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Kí ló máa ràn wá lọ́wọ́? Ka Fílípì 1:10, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Lérò tìẹ, kí ni “àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù” nígbèésí ayé ẹni?
Báwo lo ṣe lè fi hàn pé ẹ̀kọ́ Bíbélì tó ò ń kọ́ ṣe pàtàkì sí ẹ?
Tó o bá kọ́kọ́ da iyanrìn sínú ike kan kó o tó kó òkúta sínú ẹ̀, àyè ò ní gba àwọn òkúta yẹn
Tó o bá kọ́kọ́ kó òkúta sínú ike náà, wàá rí àyè tó o máa da èyí tó pọ̀ jù nínú iyanrìn náà sí. Bákan náà ló rí tó o bá fi “àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù” sípò àkọ́kọ́ nígbèésí ayé rẹ, wàá lè ṣe wọ́n láṣeyọrí, wàá sì tún rí àyè láti ṣe àwọn nǹkan míì
Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, á jẹ́ kó o mọ Ọlọ́run, kó o sún mọ́ ọn, kó o sì máa jọ́sìn rẹ̀. Ka Mátíù 5:3, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Àǹfààní wo ló máa ṣe wá tá a bá fọwọ́ pàtàkì mú ẹ̀kọ́ Bíbélì?
-
-
Yan Eré Ìnàjú Táá Múnú Jèhófà DùnGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
4. Máa fọgbọ́n lo àkókò rẹ
Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn nǹkan tí kò tọ́ kọ́ ni arákùnrin tá a rí nínú fídíò yẹn ń wò, kí ló fi hàn pé kò fọgbọ́n lo àkókò rẹ̀?
Ka Fílípì 1:10, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Báwo ni ẹsẹ Bíbélì yìí ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti máa fọgbọ́n lo àkókò wa tá a bá fẹ́ ṣe eré ìnàjú?
-