-
Ìrìbọmi Ṣe Pàtàkì!Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
3. Àwọn nǹkan wo ló yẹ kẹ́nì kan ṣe kó tó lè ṣèrìbọmi?
Tó o bá fẹ́ ṣèrìbọmi, ó ṣe pàtàkì pé kó o kọ́kọ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, kó o sì ní ìgbàgbọ́ tó lágbára nínú rẹ̀. (Ka Hébérù 11:6.) Bí ìmọ̀ rẹ ṣe ń pọ̀ sí i, tí ìgbàgbọ́ rẹ sì ń lágbára sí i, bẹ́ẹ̀ ni wàá túbọ̀ máa nífẹ̀ẹ́ Jèhófà. Ó dájú pé á máa wù ẹ́ láti sọ fún àwọn èèyàn nípa Jèhófà, wàá sì fẹ́ máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà rẹ̀ nínú ìgbésí ayé rẹ. (2 Tímótì 4:2; 1 Jòhánù 5:3) Tó o bá ti ń gbé ìgbé ayé rẹ “lọ́nà tó yẹ Jèhófà láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní kíkún,” o lè pinnu láti ya ara rẹ sí mímọ́ fún Jèhófà kó o sì ṣèrìbọmi.—Kólósè 1:9, 10.a
-
-
Ìrìbọmi Ṣe Pàtàkì!Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
a Tẹ́nì kan bá ti ṣèrìbọmi nínú ẹ̀sìn tó ń ṣe tẹ́lẹ̀, ńṣe la máa tún ìrìbọmi ṣe fún ẹni náà. Kí nìdí? Ìdí ni pé ẹ̀sìn yẹn kò kọ́ni ní ẹ̀kọ́ òtítọ́ tó wà nínú Bíbélì.—Wo Ìṣe 19:1-5 àti Ẹ̀kọ́ 13.
-
-
Ṣé O Ti Múra Tán Láti Ṣèrìbọmi?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
1. Báwo ló ṣe yẹ kí ìmọ̀ rẹ jinlẹ̀ tó kó o tó ṣèrìbọmi?
Kó o tó ṣèrìbọmi, ó yẹ kó o ní “ìmọ̀ tó péye nípa òtítọ́.” (1 Tímótì 2:4) Àmọ́, ìyẹn ò túmọ̀ sí pé o gbọ́dọ̀ mọ bí wàá ṣe fi Bíbélì dáhùn gbogbo ìbéèrè táwọn èèyàn bá ń bi ẹ́. Ó ṣe tán, àwọn tó ti ṣèrìbọmi fún ọ̀pọ̀ ọdún ṣì ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. (Kólósè 1:9, 10) Ohun tó ṣe pàtàkì jù ni pé kó o lóye àwọn ẹ̀kọ́ àkọ́kọ́bẹ̀rẹ̀ nínú Bíbélì. Àwọn alàgbà máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti mọ̀ bóyá o ti lóye àwọn ẹ̀kọ́ yìí.
-