-
Mímọrírì “Àwọn Ẹ̀bùn Tí Ó Jẹ́ Ènìyàn”Ilé Ìṣọ́—1999 | June 1
-
-
“Máa fún Wọn ní Ìkàsí Tí Ó Ju Àrà Ọ̀tọ̀ Lọ”
14, 15. (a) Gẹ́gẹ́ bí 1 Tẹsalóníkà 5:12, 13 ti wí, èé ṣe tó fi yẹ kí a ka àwọn alàgbà sí? (b) Èé ṣe táa fi lè sọ pé àwọn alàgbà ‘ń ṣiṣẹ́ kára láàárín wa’?
14 A tún lè fi hàn pé a mọrírì “àwọn ẹ̀bùn tí ó jẹ́ ènìyàn” nípa kíkà wọ́n sí. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń kọ̀wé sí ìjọ Tẹsalóníkà, ó gba àwọn mẹ́ńbà ìjọ náà níyànjú pé: “Ẹ ní ẹ̀mí ìkanisí fún àwọn tí ń ṣiṣẹ́ kára láàárín yín, tí wọ́n ń ṣe àbójútó yín nínú Olúwa, tí wọ́n sì ń ṣí yín létí; kí ẹ sì máa fún wọn ní ìkàsí tí ó ju àrà ọ̀tọ̀ lọ nínú ìfẹ́ nítorí iṣẹ́ wọn.” (1 Tẹsalóníkà 5:12, 13) “Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ kára”—àpèjúwe yẹn kò ha bá àwọn alàgbà olùfọkànsìn mu, àwọn tí ń yọ̀ǹda ara wọn fún wa tọkàntara? Tiẹ̀ ronú ná, fún ìṣẹ́jú kan, nípa ẹrù bàǹtà-banta tí àwọn arákùnrin ọ̀wọ́n wọ̀nyí ń gbé.
-
-
Mímọrírì “Àwọn Ẹ̀bùn Tí Ó Jẹ́ Ènìyàn”Ilé Ìṣọ́—1999 | June 1
-
-
16. Ṣàlàyé àwọn ọ̀nà táa lè gbà fi hàn pé a ka àwọn alàgbà sí.
16 Báwo la ṣe lè fi hàn pé a kà wọ́n sí? Òwe kan nínú Bíbélì sọ pé: “Ọ̀rọ̀ tí ó . . . bọ́ sí àkókò mà dára o!” (Òwe 15:23; 25:11) Nítorí náà, ọ̀rọ̀ ìmọrírì àti ìṣírí látọkànwá lè jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé a kò fojú tín-ín-rín iṣẹ́ àṣekára tí wọ́n ń ṣe. Pẹ̀lúpẹ̀lù, kò yẹ ká máa retí pé kí wọ́n ṣe ju ohun tí agbára wọn lè gbé. Ṣùgbọ́n ṣá o, a kò gbọ́dọ̀ tìtorí èyí lọ́tìkọ̀ láti tọ̀ wọ́n lọ fún ìrànlọ́wọ́. Ìgbà mí-ìn lè wà tí ‘ọkàn-àyà wa ń jẹ ìrora mímúná,’ táa sì nílò ìṣírí, ìtọ́sọ́nà, tàbí ìmọ̀ràn látinú Ìwé Mímọ́ látẹnu àwọn tí ó “tóótun láti kọ́ni” ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. (Sáàmù 55:4; 1 Tímótì 3:2) Lẹ́sẹ̀ kan náà, ó tún yẹ ká rántí pé alàgbà kan kò lè máa fi gbogbo àkókò ẹ̀ gbọ́ tiwa, torí pé kò lè dágunlá sí àwọn ìṣòro ìdílé tirẹ̀ tàbí àwọn ìṣòro tàwọn ẹlòmíràn nínú ìjọ. Táa bá ní “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì,” táa sì fi ìmọ̀lára yẹn hàn fún àwọn arákùnrin wọ̀nyí tí ń ṣiṣẹ́ kára, a ò ní máa béèrè ohun tí agbára wọn ò ní lè gbé lọ́wọ́ wọn. (1 Pétérù 3:8) Kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ jẹ́ ká máa fi ìmọrírì hàn fún àkókò tàbí àfiyèsí yòówù tí agbára wọn bá yọ̀ǹda fún wọn láti fún wa.—Fílípì 4:5.
17, 18. Àwọn ìrúbọ wo ni ọ̀pọ̀ àwọn aya tí ọkọ wọ́n jẹ́ alàgbà ń ṣe, báwo sì la ṣe lè fi hàn pé a kò fojú tín-ín-rín àwọn arábìnrin olóòótọ́ wọ̀nyí?
17 Tóò, ìyàwó àwọn alàgbà ńkọ́ o? Ṣé kò yẹ ká ro tàwọn náà ni? Ó ṣe tán, wọ́n ń fi ọkọ wọn sílẹ̀ kí ìjọ lè rí wọn lò. Èyí sábà máa ń béèrè pé kí wọ́n fi ọ̀pọ̀ nǹkan rúbọ. Nígbà mìíràn, ó lè di dandan káwọn alàgbà lo ọ̀pọ̀ wákàtí lálẹ́ fún bíbójútó ọ̀ràn ìjọ, bí kò bá sì jẹ́ torí èyí ni, ṣe ni wọn ì bá máa lo àkókò yẹn pẹ̀lú ìdílé wọn. Nínú ọ̀pọ̀ ìjọ, àwọn obìnrin Kristẹni olóòótọ́ múra tán láti ṣe irú ìrúbọ bẹ́ẹ̀, kí ọkọ wọn bàa lè máa bójú tó àwọn àgùntàn Jèhófà.—Fi wé 2 Kọ́ríńtì 12:15.
18 Báwo la ṣe lè fi hàn pé a kò fojú tín-ín-rín àwọn Kristẹni arábìnrin olóòótọ́ wọ̀nyí? Dájúdájú a lè fi èyí hàn nípa ṣíṣàì máa béèrè ju bó ṣe yẹ lọ lọ́wọ́ ọkọ wọn. Ṣùgbọ́n, ó dáa ká máa rántí agbára àwọn ọ̀rọ̀ ìṣírí táa lè sọ jáde lẹ́nu wẹ́rẹ́. Òwe 16:24 sọ pé: “Àwọn àsọjáde dídùnmọ́ni jẹ́ afárá oyin, ó dùn mọ́ ọkàn, ó sì ń mú àwọn egungun lára dá.” Dákun fetí sí ìrírí yìí. Lẹ́yìn ìpàdé Kristẹni lọ́jọ́ kan, tọkọtaya kan tọ alàgbà kan lọ, wọ́n sì ní àwọn fẹ́ bá a sọ̀rọ̀ nípa ọmọkùnrin àwọn tó jẹ́ ọ̀dọ́langba. Nígbà tí alàgbà náà ń bá tọkọtaya yìí sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, ìyàwó rẹ̀ mú sùúrù, ó dúró dè é. Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ wọn, ìyá ọmọ náà lọ bá ìyàwó alàgbà, ó sì sọ pé: “Mo fẹ́ dúpẹ́ lọ́wọ́ yín fún àkókò tí ọkọ yín fi ran ìdílé mi lọ́wọ́.” Ọ̀rọ̀ ìṣírí yẹn, tó jáde wẹ́rẹ́, tó sì tuni lára, wú ìyàwó alàgbà náà lórí.
-