-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—1999 | July 15
-
-
“Wàyí o, a ń pa àṣẹ ìtọ́ni fún yín, ẹ̀yin ará, . . . pé kí ẹ fà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ olúkúlùkù arákùnrin tí ń rìn ségesège, tí kì í sì í ṣe ní ìbámu pẹ̀lú àṣà àfilénilọ́wọ́ tí ẹ gbà láti ọ̀dọ̀ wa. Ní tiyín, ẹ̀yin ará, ẹ má ṣe juwọ́ sílẹ̀ ní ṣíṣe ohun tí ó tọ́. Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni kò bá jẹ́ onígbọràn sí ọ̀rọ̀ wa nípasẹ̀ lẹ́tà yìí, ẹ sàmì sí ẹni yìí, ẹ dẹ́kun bíbá a kẹ́gbẹ́, kí ojú lè tì í. Síbẹ̀, ẹ má kà á sí ọ̀tá, ṣùgbọ́n ẹ máa bá a lọ ní ṣíṣí i létí gẹ́gẹ́ bí arákùnrin.”—2 Tẹsalóníkà 3:6, 13-15.
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—1999 | July 15
-
-
Gẹ́gẹ́ bí a ti jíròrò rẹ̀ nínú 2 Tẹsalóníkà, “àwọn tí ń ṣe ségesège,” yàtọ̀ sí ipò mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tí a mẹ́nu kàn lókè yìí. Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé ‘arákùnrin’ ṣì ni àwọn wọ̀nyí, ó ní ká máa ṣí wọn létí, kí a sì máa bá wọn lò bẹ́ẹ̀. Nípa báyìí, ìṣòro tí “àwọn tí ń ṣe ségesège” ní kì í ṣe ọ̀ràn ara ẹni tó lè wáyé láàárín àwọn Kristẹni, bẹ́ẹ̀ sì ni kì í ṣe ọ̀ràn tó lágbára, tí àwọn alàgbà ìjọ lè tìtorí ẹ̀ yọni lẹ́gbẹ́, gẹ́gẹ́ bí Pọ́ọ̀lù ti ṣe nínú ọ̀ràn ti oníṣekúṣe tó wà ní Kọ́ríńtì. “Àwọn tí ń ṣe ségesège” kò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá, gẹ́gẹ́ bíi ti ọkùnrin tí wọ́n yọ lẹ́gbẹ́ níjọ Kọ́ríńtì.
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—1999 | July 15
-
-
Ó tún jẹ́ kí ìjọ mọ̀ pé yóò jẹ́ ohun yíyẹ fún wọn gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni kọ̀ọ̀kan láti ‘sàmì’ sí oníwà ségesège náà. Èyí túmọ̀ sí pé olúkúlùkù ní láti kíyè sí àwọn èèyàn tí wọ́n hu ìwà táa ti ki gbogbo ìjọ nílọ̀ nípa rẹ̀. Pọ́ọ̀lù gbà wọ́n nímọ̀ràn pé, kí wọ́n “fà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ olúkúlùkù arákùnrin tí ń rìn ségesège.” Dájúdájú, ìyẹn kò ní túmọ̀ sí pé kí wọ́n pa ẹni náà tì pátápátá, nítorí wọ́n ní láti máa ‘ṣí i létí gẹ́gẹ́ bí arákùnrin.’ Gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni, wọ́n á ṣì máa ní ìfarakanra ní ìpàdé, ó sì lè jẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́. Wọ́n á máa retí pé lọ́jọ́ ọjọ́ kan, arákùnrin wọn yóò gbọ́ ìṣílétí tí wọ́n ń fún un, yóò sì pa ìwà jágbajàgba rẹ̀ tì.
-