-
Yùníìsì àti Lọ́ìsì—Àwọn Olùkọ́ni ÀwòfiṣàpẹẹrẹIlé Ìṣọ́—1998 | May 15
-
-
Àmọ́ ṣáá o, Yùníìsì kò dá wà nínú ìgbàgbọ́ rẹ̀. Ó jọ pé Tímótì gba ìtọ́ni nínú “ìwé mímọ́” láti ọ̀dọ̀ ìyá rẹ̀ àti láti ọ̀dọ̀ ìyá ìyá rẹ̀, èyíinì ni Lọ́ìsì.a Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gba Tímótì níyànjú pé: “Máa bá a lọ nínú àwọn ohun tí o ti kọ́, tí a sì ti yí ọ lérò padà láti gbà gbọ́, ní mímọ ọ̀dọ̀ àwọn tí o ti kọ́ wọn àti pé láti ìgbà ọmọdé jòjòló ni ìwọ ti mọ ìwé mímọ́, èyí tí ó lè sọ ọ́ di ọlọ́gbọ́n fún ìgbàlà nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ ní ìsopọ̀ pẹ̀lú Kristi Jésù.”—2 Tímótì 3:14, 15.
-
-
Yùníìsì àti Lọ́ìsì—Àwọn Olùkọ́ni ÀwòfiṣàpẹẹrẹIlé Ìṣọ́—1998 | May 15
-
-
A yí Tímótì “lérò padà láti gba” àwọn òtítọ́ láti inú Ìwé Mímọ́ gbọ́. Gẹ́gẹ́ bí ìwé atúmọ̀ èdè Gíríìkì kan ti wí, ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù lò níhìn-ín túmọ̀ sí “kí a yíni lérò padà pátápátá nípa nǹkan kan; kí nǹkan kan dáni lójú.” Láìsí àní-àní, ó gba àkókò àti ìsapá tí kò kéré láti mú kí irú ìgbàgbọ́ tí ó lágbára tó bẹ́ẹ̀ ta gbòǹgbò nínú ọkàn-àyà Tímótì, kí ó ràn án lọ́wọ́ láti ronú lórí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, kí ó sì lo ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀. Fún ìdí yìí, ó hàn gbangba pé Yùníìsì àti Lọ́ìsì ṣiṣẹ́ kára láti fi Ìwé Mímọ́ kọ́ Tímótì lẹ́kọ̀ọ́. Ẹ sì wo èrè ńláǹlà tí àwọn obìnrin olùbẹ̀rù Ọlọ́run wọ̀nyí jẹ! Ó ṣeé ṣe fún Pọ́ọ̀lù láti kọ̀wé sí Tímótì pé: “Mo rántí ìgbàgbọ́ tí ó wà nínú rẹ láìsí àgàbàgebè kankan, èyí tí ó kọ́kọ́ wà nínú ìyá rẹ àgbà Lọ́ìsì àti ìyá rẹ Yùníìsì, ṣùgbọ́n èyí tí mo ní ìgbọ́kànlé pé ó wà nínú rẹ pẹ̀lú.”—2 Tímótì 1:5.
-