-
Ṣọ́ra fún Àìnígbàgbọ́Ilé Ìṣọ́—1998 | July 15
-
-
Ẹnì Kan Tí Ó Tóbi Ju Mósè
8. Nípa sísọ ohun tí a kọ sílẹ̀ nínú Hébérù 3:1, kí ni Pọ́ọ̀lù ń rọ àwọn Kristẹni ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ láti ṣe?
8 Ní mímẹ́nukan kókó pàtàkì kan, Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “Ẹ ronú nípa àpọ́sítélì àti àlùfáà àgbà tí àwa jẹ́wọ́—Jésù.” (Hébérù 3:1) Láti ‘ronú nípa nǹkan’ túmọ̀ sí “láti kíyè sí nǹkan fínnífínní . . . , láti lóye nǹkan délẹ̀délẹ̀, láti ronú nípa nǹkan dáradára.” (Vine’s Expository Dictionary of Old and New Testament Words) Nítorí náà, Pọ́ọ̀lù ń rọ àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ láti sapá gidigidi láti ní ìmọ̀ tòótọ́ nípa ipa tí Jésù kó nínú ìgbàgbọ́ àti ìgbàlà wọn. Ṣíṣe èyí yóò fún ìpinnu wọn láti dúró gbọn-in nínú ìgbàgbọ́ lókun. Kí wá ni ipa tí Jésù kó, èé sì ti ṣe tí ó fi yẹ kí a “ronú nípa” rẹ̀?
9. Èé ṣe tí Pọ́ọ̀lù fi pe Jésù ní “àpọ́sítélì” àti “àlùfáà àgbà”?
9 Pọ́ọ̀lù lo ọ̀rọ̀ náà “àpọ́sítélì” àti “àlùfáà àgbà” fún Jésù. “Àpọ́sítélì” ni ẹnì kan tí a rán jáde, níhìn-ín ó ń tọ́ka sì ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà bá aráyé sọ̀rọ̀. “Àlùfáà àgbà” ni ẹni tí àwọn ènìyàn lè tipasẹ̀ rẹ̀ bá Ọlọ́run sọ̀rọ̀. Àwọn ìpèsè méjèèjì wọ̀nyí kò ṣeé fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nínú ìjọsìn tòótọ́, Jésù sì ni ó ń ṣe méjèèjì papọ̀. Òun ni ẹni tí a rán láti ọ̀run láti kọ́ aráyé ní òtítọ́ nípa Ọlọ́run. (Jòhánù 1:18; 3:16; 14:6) Jésù tún ni ẹni náà tí a yàn gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà amápẹẹrẹṣẹ nínú ìṣètò fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ nínú tẹ́ńpìlì Jèhófà nípa tẹ̀mí. (Hébérù 4:14, 15; 1 Jòhánù 2:1, 2) Bí a bá mọrírì àwọn ìbùkún tí a lè rí gbà nípasẹ̀ Jésù ní tòótọ́, a óò ní ìgboyà láti dúró gbọn-in nínú ìgbàgbọ́, a óò sì pinnu láti ṣe bẹ́ẹ̀.
-
-
Ṣọ́ra fún Àìnígbàgbọ́Ilé Ìṣọ́—1998 | July 15
-
-
11, 12. Kí ni Pọ́ọ̀lù rọ àwọn Kristẹni, tí wọ́n jẹ́ Hébérù láti dì mú “[ṣinṣin] títí dé òpin,” báwo sì ni a ṣe lè fi ìmọ̀ràn yìí sílò?
11 Lóòótọ́, àwọn Kristẹni tí wọ́n jẹ́ Hébérù, wà ní ipò tí a ṣe ojú rere ńláǹlà sí. Pọ́ọ̀lù rán wọn létí pé wọ́n jẹ́ “alábàápín ìpè ti ọ̀run,” àǹfààní kan tí wọ́n ní láti ṣìkẹ́ ju ohunkóhun mìíràn tí ètò àwọn Júù lè fi fúnni lọ. (Hébérù 3:1) Àwọn ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù ti gbọ́dọ̀ mú kí àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró wọnnì kún fún ọpẹ́ pé àwọn jẹ́ ẹni tí ó lè rí ogún tuntun gbà dípò tí wọn yóò fi banú jẹ́ pé àwọn ti fi ohun tí ó jẹ mọ́ ogún ti àwọn Júù sílẹ̀. (Fílípì 3:8) Nígbà tí ó ń rọ̀ wọ́n láti di àǹfààní wọn mú, kí wọ́n má sì fọwọ́ yọ̀bọ́kẹ́ mú un, Pọ́ọ̀lù wí pé: “Kristi jẹ́ olùṣòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí Ọmọ lórí ilé [Ọlọ́run]. Àwa jẹ́ ilé Ẹni yẹn, bí a bá di òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ wa mú ṣinṣin àti ìṣògo wa lórí ìrètí náà ní fífìdímúlẹ̀ gbọn-in títí dé òpin.”—Hébérù 3:6.
-