ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Énọ́kù—Onígboyà Láìka Gbogbo Àtakò Sí
    Ilé Ìṣọ́—1997 | January 15
    • Ọlọ́run Mú Énọ́kù Lọ —Báwo Ni?

      Jèhófà kò jẹ́ kí Sátánì tàbí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé pa Énọ́kù. Kàkà bẹ́ẹ̀, àkọsílẹ̀ onímìísí wí pé: “Ọlọ́run mú un lọ.” (Jẹ́nẹ́sísì 5:24) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ṣàpèjúwe ọ̀ràn lọ́nà yí pé: “Nípa ìgbàgbọ́ ni a ṣí Énọ́kù nípò pa dà láti má ṣe rí ikú, a kò sì rí i níbi kankan nítorí tí Ọlọ́run ti ṣí i nípò pa dà; nítorí ṣáájú ìṣínípòpadà rẹ̀ ó ní ẹ̀rí náà pé ó ti wu Ọlọ́run dáadáa.”—Hébérù 11:5.

      Báwo ni a ṣe “ṣí Énọ́kù nípò pa dà láti má ṣe rí ikú”? Tàbí gẹ́gẹ́ bí a ṣe túmọ̀ rẹ̀ nínú ìtúmọ̀ tí R. A. Knox ṣe, báwo ni a ṣe “mú” Énọ́kù “lọ láìnírìírí ikú”? Ọlọ́run fòpin sí ìwàláàyè Énọ́kù lọ́nà àlàáfíà, ní gbígbà á kúrò lọ́wọ́ ìrora ikú tí àìsàn tàbí tí ìwà ipá láti ọwọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀ lè fà. Bẹ́ẹ̀ ni, Jèhófà ké ìwàláàyè Énọ́kù kúrú ní ẹni ọdún 365—ó jẹ́ ọ̀dọ́ gidigidi ní ìfiwéra pẹ̀lú àwọn alájọgbáyé rẹ̀.

      Báwo ní a ṣe fún Énọ́kù ní “ẹ̀rí . . . pé ó ti wu Ọlọ́run dáadáa”? Ẹ̀rí wo ni ó ní? Ó ṣeé ṣe pé, Ọlọ́run mú kí Énọ́kù bọ́ sí ojúran, àní bí a ṣe “gba” àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù “lọ,” tàbí tí a ṣí i nípò pa dà, tí ó hàn gbangba pé ó ń rí ìran nípa párádísè tẹ̀mí ọjọ́ ọ̀la ti ìjọ Kristẹni. (Kọ́ríńtì Kejì 12:3, 4) Ìjẹ́rìí, tàbí ẹ̀rí pé Énọ́kù wu Ọlọ́run ti ní láti kan rírí ìran fìrí nípa Párádísè ilẹ̀ ayé ti ọjọ́ ọ̀la níbi tí gbogbo àwọn tí ń gbé ibẹ̀ yóò ti ti ipò ọba aláṣẹ Ọlọ́run lẹ́yìn. Bóyá nígbà tí Énọ́kù ń nírìírí ìran arùmọ̀lára-sókè kan ni Ọlọ́run mú un lọ nínú ikú aláìnírora láti sùn títí di ọjọ́ àjíǹde rẹ̀. Ó dà bíi pé, bí ó ti rí nínú ọ̀ràn Mósè, Jèhófà palẹ̀ òkú Énọ́kù mọ́, nítorí “a kò . . . rí i níbi kankan.”—Hébérù 11:5; Diutarónómì 34:5, 6; Júúdà 9.

  • Énọ́kù—Onígboyà Láìka Gbogbo Àtakò Sí
    Ilé Ìṣọ́—1997 | January 15
    • Énọ́kù Ha Lọ sí Ọ̀run Bí?

      “Nípa ìgbàgbọ́ ni a ṣí Énọ́kù nípò pa dà láti má ṣe rí ikú.” Nígbà tí wọ́n ń túmọ̀ apá ibí yìí nínú Hébérù 11:5, àwọn ìtúmọ̀ Bíbélì kan fi hàn pé Énọ́kù kò kú ní ti gidi. Fún àpẹẹrẹ, A New Translation of the Bible, láti ọwọ́ James Moffatt, wí pé: “Nípa ìgbàgbọ́ ni a fi mú Énọ́kù lọ sí ọ̀run tí kò fi kú rárá.”

      Ṣùgbọ́n, ní nǹkan bí 3,000 ọdún lẹ́yìn ọjọ́ Énọ́kù, Jésù Kristi wí pé: “Kò sí ènìyàn kankan tí ó ti gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó sọ̀ kalẹ̀ láti ọ̀run, Ọmọkùnrin ènìyàn.” (Jòhánù 3:13) Ìtúmọ̀ The New English Bible kà pé: “Kò sí ẹni tí ó lọ sí òkè ọ̀run rí àyàfi ẹni tí ó ti ọ̀run sọ kalẹ̀ wá, Ọmọkùnrin Ènìyàn.” Nígbà tí Jésù fi sọ gbólóhùn yẹn, kò tilẹ̀ tí ì gòkè re ọ̀run.—Fi wé Lúùkù 7:28.

      Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé Énọ́kù àti àwọn mìíràn tí wọ́n para pọ̀ jẹ́ àwọ sánmà ńlá ti àwọn ẹlẹ́rìí ṣáájú àkókò àwọn Kristẹni lápapọ̀ “kú” wọn “kò rí ìmúṣẹ ìlérí náà gbà.” (Hébérù 11:13, 39) Èé ṣe? Nítorí pé gbogbo ẹ̀dá ènìyàn, títí kan Énọ́kù, ti jogún ẹ̀ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Ádámù. (Orin Dáfídì 51:5; Róòmù 5:12) Ọ̀nà kan ṣoṣo sí ìgbàlà jẹ́ nípasẹ̀ ẹbọ ìràpadà Kristi Jésù. (Ìṣe 4:12; Jòhánù Kíní 2:1, 2) Ní ọjọ́ Énọ́kù, a kò tí ì san ìràpadà yẹn. Nítorí náà, Énọ́kù kò lọ sí ọ̀run, ṣùgbọ́n ó ń sùn nínú ikú ní dídúró de àjíǹde lórí ilẹ̀ ayé.—Jòhánù 5:28, 29.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́