-
Wò Kọjá Ohun Tí O rí!Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | February 15
-
-
Yàtọ̀ sí ìpọ́njú àwọn ẹlòmíràn, Jesu rí tirẹ̀ pẹ̀lú. (Heberu 5:7‚ 8) Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ojú ìríran tẹ̀mí pípé, ó wò ré kọjá wọn láti rí èrè dídi ẹni tí a gbé ga sí ìwàláàyè àìleèkú nítorí ipa ọ̀nà ìwàtítọ́ rẹ̀. Nígbà náà gẹ́gẹ́ bíi Messia Ọba, yóò ní àǹfààní láti gbé ìran aráyé tí a ti pọ́n lójú ga kúrò nínú ipò ìdibàjẹ́ sí ìjẹ́pípé tí Jehofa pète láti ìpilẹ̀ṣẹ̀. Títẹ̀ tí ó tẹjú mọ́ àwọn ìfojúsọ́nà ọjọ́ iwájú wọ̀nyí ràn án lọ́wọ́ láti di ayọ̀ nínú iṣẹ́ ìsìn Ọlọrun mú láìka àwọn ìpọ́njú tí ó ń rí láti ọjọ́ dé ọjọ́ sí. Paulu kọ̀wé lẹ́yìn náà pé: “Nitori ìdùnnú-ayọ̀ tí a gbéka iwájú rẹ̀ ó farada òpó igi oró, ó tẹ́ḿbẹ́lú ìtìjú, ó sì ti jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọlọrun.”—Heberu 12:2.
-
-
Wò Kọjá Ohun Tí O rí!Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | February 15
-
-
Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ nípa ohun tí ó ran Jesu lọ́wọ́ láti fara dà, Paulu tún tọ́ka sí ipa ọ̀nà náà fún wa nígbà tí ó kọ̀wé pé: “Ẹ . . . jẹ́ kí a fi ìfaradà sá eré-ìje tí a gbéka iwájú wa, bí a ti ń fi tọkàntara wo Olórí Aṣojú ati Aláṣepé ìgbàgbọ́ wa, Jesu.” (Heberu 12:1‚ 2) Bẹ́ẹ̀ ni, láti tẹ̀ lé ipa ọ̀nà Kristian pẹ̀lú àṣeyọrí àti ayọ̀, a gbọ́dọ̀ wò ré kọjá àwọn nǹkan tí ó wà níwájú wa nísinsìnyí. Ṣùgbọ́n báwo ni a ṣe ń fi “tọkàntara wo” Jesu, kí sì ni yóò ṣe fún wa?
Gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ, ní 1914, a gbé Jesu gorí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọrun, ó sì ń ṣàkóso láti ọ̀run. Dájúdájú, gbogbo èyí ni a kò lè fi ojú ìyójú wa rí. Síbẹ̀, bí a bá fi “tọkàntara wo” Jesu, ojú ìríran wa nípa tẹ̀mí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti rí i pé ó ti ṣe tán láti gbé ìgbésẹ̀ láti mú òpin dé bá ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan búburú ìsinsìnyí, kí ó sì gbé Satani àti àwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀ sọ sínú ìdè àìlèṣiṣẹ́mọ́. Bí a bá tilẹ̀ wò síwájú sí i, agbára ìríran wa nípa tẹ̀mí yóò ṣí ayé tuntun àgbàyanu náà payá, nínú èyí tí “ikú kì yoo sì sí mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yoo sí ọ̀fọ̀ tabi igbe ẹkún tabi ìrora mọ́. Awọn ohun àtijọ́ ti kọjá lọ.”—Ìṣípayá 19:11-16; 20:1-3; 21:4.
Nítorí náà, dípò dídi ẹni tí àwọn ìpọ́njú tí yóò wà fún ìgbà díẹ̀ tí à báà dojú kọ lójoojúmọ́ di ẹrù pa, èé ṣe tí a kò tẹjú wa mọ́ àwọn nǹkan tí yóò wà títí láé? Pẹ̀lú ojú ìgbàgbọ́, èé ṣe tí a kò wò ré kọjá àìsàn àti ìwọra tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé tí a ti bàjẹ́ yìí, láti lè rí paradise tí ó kún fún àwọn ènìyàn onílera, aláyọ̀, tí wọ́n sì bìkítà? Èé ṣe tí a kò wò ré kọjá àwọn àbàwọ́n ara wa, nípa tara àti nípa tẹ̀mí, kí a sì rí ara wa ní ẹni tí ó bọ́ lọ́wọ́ wọn títí ayérayé nípasẹ̀ àǹfààní ẹbọ ìràpadà Kristi? Èé ṣe tí o kò wò ré kọjá àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú tí ogun, ìwà ipá àti ìwà ọ̀daràn fi sílẹ̀, kí o sì rí àwọn ẹni tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ jí dìde tí a ń dá lẹ́kọ̀ọ́ nínú àlàáfíà àti òdodo Jehofa?
Ní àfikún, láti fi “tọkàntara wo” Jesu yóò tún kan títẹ ojú ìríran wa nípa tẹ̀mí mọ́ ohun tí Ìjọba náà ti ṣàṣeparí rẹ̀ láàárín àwọn ènìyàn Ọlọrun lórí ilẹ̀ ayé: ìṣọ̀kan, àlàáfíà, ìfẹ́, ìfẹ́ni ará, àti aásìkí nípa tẹ̀mí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò lè fojú rí i. Kristian obìnrin kan ní Germany, lẹ́yìn tí ó wo fídíò náà, United by Divine Teaching, kọ̀wé pé: “Fídíò náà yóò ràn mí lọ́wọ́ láti túbọ̀ máa fi sọ́kàn pé ọ̀pọ̀ àwọn Kristian arákùnrin àti arábìnrin jákèjádò ayé ń ṣiṣẹ́ sin Jehofa pẹ̀lú ìdúróṣinṣin ní lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí—wọ́n sì ń ṣe bẹ́ẹ̀ láìka àtakò gbogbogbòò sí. Ẹ wo bí ìṣọ̀kan ará ti ṣeyebíye tó nínú ayé oníwà ipá àti oníkòórìíra!”
Ìwọ pẹ̀lú ha “rí” Jehofa, Jesu, àti àwọn áńgẹ́lì olùṣòtítọ́, àti àràádọ́ta ọ̀kẹ́ àwọn Kristian ẹlẹgbẹ́ rẹ, tí wọ́n dúró sí ẹ̀gbẹ́ rẹ bí? Bí bẹ́ẹ̀ bá ni, o kò ní ṣàníyàn jù nípa “àníyàn ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan yii” tí ó lè mú ọ dúró gbagidi pẹ̀lú ìrẹ̀wẹ̀sì, kí ó sì mú kí o di “aláìléso” nínú iṣẹ́ ìsìn Kristian. (Matteu 13:22) Nítorí náà, fi “tọkàntara wo” Jesu nípa títẹ ojú tẹ̀mí rẹ mọ́ Ìjọba Ọlọrun tí a ti fìdí rẹ̀ kalẹ̀ àti àwọn ìbùkún rẹ̀, nísinsìnyí àti ní ọjọ́ iwájú.
-