-
Ohun Tí Bíbélì Sọ Nípa Iṣẹ́ àti OwóGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
2. Kí ni Bíbélì sọ nípa owó?
Òótọ́ ni pé Bíbélì sọ pé ‘owó jẹ́ ààbò.’ Àmọ́ ó tún jẹ́ ká mọ̀ pé owó nìkan ò lè fún wa láyọ̀. (Oníwàásù 7:12) Ìdí nìyẹn tí Bíbélì fi gbà wá níyànjú pé ká ‘jẹ́ kí àwọn nǹkan tó wà báyìí tẹ́ wa lọ́rùn.’ (Ka Hébérù 13:5.) Tá a bá ní ìtẹ́lọ́rùn pẹ̀lú àwọn ohun tá a ní, a ò ní kóra wa sí wàhálà torí pé a ṣáà fẹ́ ní nǹkan púpọ̀ sí i. Yàtọ̀ síyẹn, a ò ní lọ jẹ gbèsè láìjẹ́ pé ó pọn dandan. (Òwe 22:7) A ò sì ní máa ta tẹ́tẹ́, tàbí ká kó ara wa síṣòro níbi tá a ti ń wá bá a ṣe máa dolówó òjijì.
-
-
Ohun Tí Bíbélì Sọ Nípa Iṣẹ́ àti OwóGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. A máa jàǹfààní púpọ̀ tá a bá ní ìtẹ́lọ́rùn
Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń wá bí wọ́n ṣe máa lówó rẹpẹtẹ. Àmọ́ ohun tí Bíbélì sọ yàtọ̀ síyẹn. Ka 1 Tímótì 6:6-8, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Kí ni Bíbélì gbà wá níyànjú pé ká ṣe?
Tá ò bá tiẹ̀ lówó púpọ̀, a lè láyọ̀. Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ìdílé yìí ò fi bẹ́ẹ̀ lówó lọ́wọ́, kí ló ń fún wọn láyọ̀?
Tá a bá ní gbogbo ohun tá a nílò, àmọ́ tá a tún ń wá bá a ṣe máa ní sí i ńkọ́? Jésù jẹ́ ká mọ àkóbá tí èyí lè ṣe. Ka Lúùkù 12:15-21, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Kí lo rí kọ́ látinú àpèjúwe yẹn?—Wo ẹsẹ 15.
Ka Òwe 10:22 àti 1 Tímótì 6:10 kó o sì fi wéra wọn. Lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Ṣé kéèyàn sún mọ́ Ọlọ́run ló ṣe pàtàkì jù ni àbí kéèyàn lówó rẹpẹtẹ? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?
Téèyàn bá ń wá owó lójú méjèèjì, ìṣòro wo nìyẹn lè fà?
-