-
Ṣé O Ti Wọnú Ìsinmi Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2011 | July 15
-
-
“Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Yè”
20. Ọ̀nà méjì wo la lè gbà lóye ohun tó wà nínú Hébérù 4:12? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
20 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé “ọ̀rọ̀ ọlọ́run yè,” kì í ṣe Bíbélì ló ń tọ́ka sí ní tààràtà.c Àwọn ẹsẹ míì nínú orí yẹn fi hàn pé ìlérí Ọlọ́run ni Pọ́ọ̀lù ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ohun tó sì ń sọ ni pé lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá ti ṣèlérí ohun kan, kì í gbàgbé ìlérí tó ṣe. Nípasẹ̀ wòlíì Aísáyà, Jèhófà sọ nípa ọ̀rọ̀ tó bá ti ẹnu rẹ̀ jáde pé: “Ọ̀rọ̀ mi . . . kì yóò padà sọ́dọ̀ mi láìní ìyọrísí, ṣùgbọ́n . . . yóò sì ní àṣeyọrí sí rere tí ó dájú nínú èyí tí mo tìtorí rẹ̀ rán an.” (Aísá. 55:11) Torí náà, kò sí ìdí fún wa láti máa kánjú bí Ọlọ́run kò bá mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ nígbà tá a fọkàn sí. Jèhófà ‘ń bá a nìṣó láti máa ṣiṣẹ́’ kó bàa lè ṣe àṣeparí àwọn ohun tó ní lọ́kàn.—Jòh. 5:17.
21. Báwo ni ohun tó wà nínú Hébérù 4:12 ṣe lè fún àwọn tó ti dàgbà lára àwọn “ogunlọ́gọ̀ ńlá” ní ìṣírí?
21 Ọjọ́ pẹ́ tí àwọn tó ti dàgbà lára àwọn “ogunlọ́gọ̀ ńlá” ti ń sin Jèhófà láìyẹsẹ̀. (Ìṣí. 7:9) Ọ̀pọ̀ lára wọn kò lérò pé àwọn máa darúgbó nínú ètò àwọn nǹkan yìí. Síbẹ̀, wọn kò rẹ̀wẹ̀sì. (Sm. 92:14) Wọ́n mọ̀ pé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè àti pé àwọn ìlérí rẹ̀ kò ní ṣaláì ní ìmúṣẹ. Wọ́n sì tún mọ̀ pé Jèhófà ń ṣiṣẹ́ kó bàa lè mú àwọn ìlérí rẹ̀ ṣẹ. Níwọ̀n bí Ọlọ́run sì ti máa ń fi ọwọ́ pàtàkì mú àwọn ohun tó fẹ́ ṣe, inú rẹ̀ máa ń dùn bí àwa náà bá fọwọ́ pàtàkì mú un. Ní ọjọ́ keje tí Jèhófà fi ń sinmi yìí, kò sí ohunkóhun tó máa dá a dúró láti mú àwọn ìlérí rẹ̀ ṣẹ, ó sì mọ̀ pé àwọn èèyàn òun lápapọ̀ á fọwọ́ sowọ́ pọ̀ pẹ̀lú òun. Ìwọ ńkọ́? Ṣé o ti wọnú ìsinmi Ọlọ́run?
-
-
Ṣé O Ti Wọnú Ìsinmi Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2011 | July 15
-
-
c Lónìí, Ọlọ́run máa ń lo Ọ̀rọ̀ rẹ̀, tó lè yí ìgbésí ayé wa pa dà, láti bá wa sọ̀rọ̀. Torí náà, ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ nínú Hébérù 4:12 yìí tún kan Bíbélì.
-