-
“Àánú Ṣe É”“Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
Máa fi “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì hàn”
7. Kí ló lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní ìyọ́nú, ọ̀nà wo la sì lè gbà fi hàn pé oníyọ̀ọ́nú èèyàn ni wá?
7 Ó yẹ káwa Kristẹni máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú fífi ọ̀rọ̀ àwọn ẹlòmíì ro ara wa wò. Bíbélì rọ̀ wá pé ká máa fi “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì hàn.”b (1 Pétérù 3:8) Ó lè má rọrùn láti mọ bó ṣe ń ṣe àwọn tí àìsàn líle ń bá fínra tàbí àwọn tí wọ́n ní ìsoríkọ́, pàápàá bí irú rẹ̀ ò bá tíì ṣe wá rí. Máa rántí pé kò dìgbà téèyàn bá nírú ìṣòro tẹ́nì kan ní kéèyàn tó lè káàánú irú ẹni bẹ́ẹ̀. Jésù fọ̀rọ̀ àwọn aláìsàn ro ara ẹ̀ wò, bẹ́ẹ̀ sì rèé òun ò ṣàìsàn rí. Báwo làwa náà ṣe lè wá kọ́ bá a ṣe máa fọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ro ara wa wò? A lè ṣe bẹ́ẹ̀ nípa fífetísílẹ̀ dáadáa nígbà táwọn tójú ń pọ́n bá ń sọ ohun tó wà lọ́kàn wọn àti ohun tó ń ṣe wọ́n. A lè bi ara wa pé, ‘Bó bá jẹ́ pé èmi ni mo nírú ìṣòro yìí, kí ni màá ṣe?’ (1 Kọ́ríńtì 12:26) Bá a bá jẹ́ ẹni tó tètè ń kíyè sí ìṣesí àwọn èèyàn, ó máa rọrùn fún wa láti “máa sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ọkàn tí ó soríkọ́.” (1 Tẹsalóníkà 5:14) Nígbà míì, tá a bá fi ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ro ara wa wò, omijé á gbọ̀n wá, á ṣe wá kọjá ká kàn máa sọ̀rọ̀. Róòmù 12:15 sọ pé: “Ẹ máa sunkún pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ń sunkún.”
-
-
“Àánú Ṣe É”“Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
b Ọ̀rọ̀ àpọ́nlé lédè Gíríìkì tó túmọ̀ sí “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì” ṣeé tú ní olówuuru sí “bá jìyà.”
-