ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìlú Ológo
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 9. Báwo ni Jòhánù ṣe ṣàpèjúwe àwọn nǹkan ìkọ́lé tí wọ́n fi kọ́ ìlú náà?

      9 Jòhánù ń bá àpèjúwe rẹ̀ lọ pé: “Wàyí o, ìgbékalẹ̀ ògiri rẹ̀ jẹ́ òkúta jásípérì, ìlú ńlá náà sì jẹ́ ògidì wúrà bí gíláàsì tí ó mọ́ kedere. Àwọn ìpìlẹ̀ ògiri ìlú ńlá náà ni a fi gbogbo onírúurú òkúta ṣíṣeyebíye ṣe lọ́ṣọ̀ọ́: ìpìlẹ̀ kìíní jẹ́ jásípérì, ìkejì sàfáyà, ìkẹta kásídónì, ìkẹrin ẹ́mírádì, ìkarùn-ún sádónísì, ìkẹfà sádíọ́sì, ìkeje kírísóláítì, ìkẹjọ bérílì, ìkẹsàn-án tópásì, ìkẹwàá kírísópírásì, ìkọkànlá háyásíǹtì, ìkejìlá ámétísì. Pẹ̀lúpẹ̀lù, ẹnubodè méjìlá náà jẹ́ péálì méjìlá; ọ̀kọ̀ọ̀kan ẹnubodè náà ni a fi péálì kan ṣe. Ọ̀nà fífẹ̀ ìlú ńlá náà sì jẹ́ ògidì wúrà, bí gíláàsì tí ń fi òdì-kejì hàn kedere.”—Ìṣípayá 21:18-21.

  • Ìlú Ológo
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 12. Kí ni (a) òkúta iyebíye ni Jèhófà fi ṣe àwọn ìpìlẹ̀ ìlú náà méjèèjìlá lọ́ṣọ̀ọ́ fi hàn? (b) jíjẹ́ tí àwọn ibodè ìlú náà jẹ́ péálì fi hàn?

      12 Kódà àwọn ìpìlẹ̀ ìlú náà lẹ́wà, níwọ̀n bó ti jẹ́ pé òkúta ṣíṣeyebíye méjìlá ni Jèhófà fi ṣe wọ́n lọ́ṣọ̀ọ́. Èyí múni rántí àlùfáà àgbà àwọn Júù látijọ́, láwọn ọjọ́ ayẹyẹ, ó máa ń wọ ẹ̀wù éfódì kan tí wọ́n to òkúta ṣíṣeyebíye méjìlá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ sí lára, èyí dà bí ẹní jọ àwọn ohun tí Jòhánù ń ṣàpèjúwe yìí. (Ẹ́kísódù 28:15-21) Ó dájú pé èyí ò ṣèèṣì jọra! Kàkà bẹ́ẹ̀, ó jẹ́ ká rí iṣẹ́ àlùfáà Jerúsálẹ́mù Tuntun, èyí tí Jésù, Àlùfáà Àgbà ńlá náà, jẹ́ “fìtílà” fún. (Ìṣípayá 20:6; 21:23; Hébérù 8:1) Bákan náà, nípasẹ̀ Jerúsálẹ́mù Tuntun làwọn àǹfààní iṣẹ́ Jésù, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà àgbà fi ń nasẹ̀ dé ọ̀dọ̀ aráyé. (Ìṣípayá 22:1, 2) Ibodè méjìlá ìlú náà, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan rẹ̀ jẹ́ péálì tí ẹwà ẹ̀ jojú ní gbèsè, ránni létí àkàwé tí Jésù fi fi Ìjọba Ọlọ́run wé péálì iyebíye kan. Gbogbo àwọn tó ń gba ẹnu ibodè wọ̀nyẹn wọlé ti ní láti máa fi ojúlówó ìmọrírì hàn fáwọn ohun tẹ̀mí.—Mátíù 13:45, 46; fi wé Jóòbù 28:12, 17, 18.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́